Fò sí àkóónú

circa 1406–1380 BC

Conquest of Canaan

Joshua leads Israel across the Jordan into the promised land, defeating the Canaanite kingdoms one by one.

658 ẹsẹ · 1 ìwé tí a bo

Àwọn ẹsẹ láti sáà yìí

  1. Joṣua 19:6nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Beti-Lebaoti àti Ṣarueli, ìlú wọn jẹ́ mẹ́tàlá àti ìletò wọn.

  2. Joṣua 19:7nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Aini, Rimoni, Eteri àti Aṣani, ìlú wọn jẹ́ mẹ́rin àti ìletò wọn,

  3. Joṣua 19:8nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    àti gbogbo àwọn agbègbè ìlú wọ̀nyí títí dé Baalati-Beeri (Rama ní gúúsù). Èyí ni ilẹ̀ ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Simeoni, agbo ilé, ní agbo ilé.

  4. Joṣua 19:9nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    A mú ogún ìní àwọn ọmọ Simeoni láti ìpín Juda, nítorí ìpín Juda pọ̀ ju èyí tí wọ́n nílò lọ. Báyìí ni àwọn ọmọ Simeoni gba ìní wọn ní àárín ilẹ̀ Juda.

  5. Joṣua 19:10nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Kèké kẹta jáde fún Sebuluni, ní agbo ilé ní agbo ilé ààlà ìní wọn sì lọ títí dé Saridi.

  6. Joṣua 19:11nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Ó sì lọ sí ìwọ̀-oòrùn ní Marala, ó sì dé Dabbeṣeti, ó sì lọ títí dé odo ní ẹ̀bá Jokneamu.

  7. Joṣua 19:12nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Ó sì yípadà sí ìlà-oòrùn láti Saridi sí ìhà ìlà-oòrùn dé ilẹ̀ Kisiloti-Tabori, ó sì lọ sí Daberati, ó sì gòkè lọ sí Jafia.

  8. Joṣua 19:13nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Nígbà náà ní o lọ sí ìhà ìlà-oòrùn lọ sí Gati-Heferi àti Eti-Kaṣini, ó sì jáde ní Rimoni, ó sì yí sí ìhà Nea.

  9. Joṣua 19:14nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Ní ibẹ̀, ààlà sì yíká ní ìhà àríwá lọ sí Hnatoni ó sì pín ní àfonífojì Ifita-Eli.

  10. Joṣua 19:15nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Lára wọn ni Katati, Nahalali, Ṣimroni, Idala àti Bẹtilẹhẹmu. Wọ́n sì jẹ́ ìlú méjìlá àti ìletò wọn.

  11. Joṣua 19:16nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn jẹ́ ìní Sebuluni, ní agbo ilé agbo ilé.

  12. Joṣua 19:17nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Kèké kẹrin jáde fún Isakari, agbo ilé ní agbo ilé.

  13. Joṣua 19:18nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Lára ilẹ̀ wọn ni èyí: Jesreeli, Kesuloti, Ṣunemu,

  14. Joṣua 19:19nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Hafraimu, Ṣihoni, Anaharati,

  15. Joṣua 19:20nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Rabiti, Kiṣioni, Ebesi,

  16. Joṣua 19:21nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Remeti, Eni-Gannimu, Eni-Hada àti Beti-Pasesi.

  17. Joṣua 19:22nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Ààlà náà sì dé Tabori, Ṣahasuma, àti Beti-Ṣemeṣi, ó sì pin ní Jordani. Wọ́n sì jẹ́ ìlú mẹ́rìndínlógún àti ìletò wọn.

  18. Joṣua 19:23nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn jẹ́ ìní ẹ̀yà Isakari, ní agbo ilé agbo ilé.

  19. Joṣua 19:24nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Kèké karùn-ún jáde fún ẹ̀yà Aṣeri, ní agbo ilé agbo ilé.

  20. Joṣua 19:25nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Lára ilẹ̀ wọn ni èyí: Helikati, Hali, Beteni, Akṣafu,

  21. Joṣua 19:26nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Allameleki, Amadi, àti Miṣali. Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ààlà náà dé Karmeli àti Ṣihori-Libinati.

  22. Joṣua 19:27nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Nígbà náà ni o yí sí ìhà ìlà-oòrùn Beti-Dagoni, dé Sebuluni àti àfonífojì Ifita-Eli, ó sì lọ sí àríwá sí Beti-Emeki àti Neieli, ó sì kọjá lọ sí Kabulu ní apá òsì.

  23. Joṣua 19:28nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Ó sì lọ sí Abdoni, Rehobu, Hammoni àti Kana títí dé Sidoni ńlá.

  24. Joṣua 19:29nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Ààlà náà sì tẹ̀ sí ìhà Rama, ó sì lọ sí ìlú olódi Tire, ó sì yà sí Hosa, ó sì jáde ní Òkun Ńlá ní ilẹ̀ Aksibu,

  25. Joṣua 19:30nǹkan bí 1443 ṣáájú Kristi

    Uma, Afeki àti Rehobu. Wọ́n sì jẹ́ ìlú méjìlélógún àti ìletò wọn.