Fò sí àkóónú

circa AD 48–96

Letters to the Churches

Paul and other apostles write to strengthen, correct, and encourage the scattered churches across the Roman world.

2,767 ẹsẹ · 21 ìwé tí a bo

Àwọn ẹsẹ láti sáà yìí

Sẹ́ nípa ìwé
  1. Romu 3:15nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    “Ẹsẹ̀ wọn yára láti ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀,

  2. Romu 3:16nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    ìparun àti ìpọ́njú wà lọ́nà wọn.

  3. Romu 3:17nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    Ọ̀nà àlàáfíà ni wọn kò sì mọ̀,”

  4. Romu 3:18nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    “Ìbẹ̀rù Ọlọ́run kò sí níwájú wọn.”

  5. Romu 3:19nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    Àwa sì mọ̀ pé ohunkóhun tí òfin bá wí, ó ń wí fún àwọn tí ó wà lábẹ́ òfin: kí gbogbo ẹnu bá à lè dákẹ́ àti kí a lè mú gbogbo aráyé wá sábẹ́ ìdájọ́ Ọlọ́run.

  6. Romu 3:20nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    Nítorí pé nípa iṣẹ́ òfin, a kì yóò dá ẹnikẹ́ni láre níwájú rẹ̀: nítorí nípa òfin ni ìmọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ ti wá.

  7. Romu 3:21nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, a ti fi òdodo Ọlọ́run hàn láìsí òfin, tí a ti ń jẹ́rìí sí nípa òfin àti nípa àwọn wòlíì,

  8. Romu 3:22nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    àní òdodo Ọlọ́run nípa ìgbàgbọ́ nínú Jesu Kristi, sí gbogbo ènìyàn àti gbogbo àwọn tí ó gbàgbọ́, nítorí tí kò sí ìyàtọ̀ láàrín Júù àti Helleni.

  9. Romu 3:23nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    Gbogbo ènìyàn ni ó ṣá ti ṣẹ̀, tí wọ́n sì kùnà ògo Ọlọ́run,

  10. Romu 3:24nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    àwọn ẹni tí a ń dá láre lọ́fẹ̀ẹ́ nípa oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀, nípa ìdáǹdè tí ó wà nínú Kristi Jesu.

  11. Romu 3:25nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    Ẹni tí Ọlọ́run ti gbé kalẹ̀ láti jẹ́ ètùtù nípa ìgbàgbọ́ nípa ẹ̀jẹ̀ rẹ̀, láti fi òdodo rẹ̀ hàn nítorí ìdáríjì àwọn ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti kọjá, nínú ìpamọ́ra Ọlọ́run,

  12. Romu 3:26nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    láti fi òdodo rẹ̀ hàn ní ìgbà ìsinsin yìí: kí ó lè jẹ́ olódodo àti olùdáláre ẹni tí ó gba Jesu gbọ́.

  13. Romu 3:27nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    Ọ̀nà ìṣògo dà? A ti mú un kúrò. Nípa òfin wo? Nípa iṣẹ́? Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n nípa òfin ìgbàgbọ́.

  14. Romu 3:28nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    Nítorí náà, a parí rẹ̀ sí pé nípa ìgbàgbọ́ ni a ń dá ènìyàn láre láìsí iṣẹ́ òfin.

  15. Romu 3:29nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    Ọlọ́run àwọn Júù nìkan ha ni bí? Kì í ha ṣe ti àwọn aláìkọlà pẹ̀lú? Bẹ́ẹ̀ ni, ti àwọn aláìkọlà pẹ̀lú.

  16. Romu 3:30nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    Bí ó ti jẹ́ pé Ọlọ́run kan ni, yóò dá àwọn akọlà láre nípa ìgbàgbọ́ àti àwọn aláìkọlà nípa ìgbàgbọ́ wọn.

  17. Romu 3:31nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    Àwa ha ń sọ òfin dasán nípa ìgbàgbọ́ bí? Kí a má rí i, ṣùgbọ́n a ń fi òfin múlẹ̀.

  18. Romu 4:1nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    Ǹjẹ́ kín ni àwa ó ha wí nípa Abrahamu, baba wa ti o ṣàwárí èyí? Májẹ̀mú láéláé jẹ́rìí sí i wí pé, a gba Abrahamu là nípa ìgbàgbọ́.

  19. Romu 4:2nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    Nítorí bí a bá dá Abrahamu láre nípa iṣẹ́, ó ní ohun ìṣògo; ṣùgbọ́n kì í ṣe níwájú Ọlọ́run.

  20. Romu 4:3nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    Ìwé Mímọ́ ha ti wí? “Abrahamu gba Ọlọ́run gbọ́, a sì kà á sí òdodo fún un.”

  21. Romu 4:4nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    Ǹjẹ́ fún ẹni tí ó ṣiṣẹ́, a kò ka èrè náà sí oore-ọ̀fẹ́ bí kò ṣe sí ẹ̀tọ́ rẹ̀.

  22. Romu 4:5nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    Ṣùgbọ́n fún ẹni tí kò ṣiṣẹ́, tí ó sì ń gba ẹni tí ó ń dá ènìyàn búburú láre gbọ́, a ka ìgbàgbọ́ rẹ̀ sí òdodo.

  23. Romu 4:6nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    Gẹ́gẹ́ bí Dafidi pẹ̀lú ti pe olúwa rẹ̀ náà ní ẹni ìbùkún, ẹni tí Ọlọ́run ka òdodo fún láìsí ti iṣẹ́.

  24. Romu 4:7nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    Wí pé, “Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí a dárí ìrékọjá wọn jì, tí a sì bo ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́lẹ̀.

  25. Romu 4:8nǹkan bí 60 lẹ́yìn Kristi

    Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà ẹni tí Olúwa kò ka ẹ̀ṣẹ̀ sí lọ́rùn.”