- English
- King James KJV
- Complete Jewish CJB
- World English WEBM
- Berean Standard BSB
- American Standard ASV
- Geneva GNV
- Young's Literal YLT
- Douay-Rheims DRC
- International
- Shqip ALB
- العربية SVD
- বাংলা BN-IRV
- မြန်မာ Judson
- 简体文 CUV-S
- 繁體中文 CUV-T
- Čeština BKR
- Nederlands STVE
- Français LSG
- Deutsch SCH
- Ελληνικά Vamvas
- ગુજરાતી GU-IRV
- Hausa HCB
- עברית Hebrew
- हिन्दी HCV
- Magyar KAROLI
- Bahasa Indonesia INDO-TB
- Italiano Diodati
- 日本語 Kougo
- 한국어 Korean
- മലയാളം MAL
- मराठी MRCV
- Norsk DNB
- فارسی OPV
- Polski BG
- Português Almeida
- Română Cornilescu
- Русский Synodal
- Español RVG
- Kiswahili Neno
- Svenska SV1917
- Tagalog TAG-ADB
- தமிழ் TCV
- తెలుగు TSA
- ภาษาไทย THAI-KJV
- Українська Ohienko
- Tiếng Việt CADMAN
- Yorùbá YCB
circa 605–538 BC
The Babylonian Exile
Jerusalem falls and the temple burns; Ezekiel and Daniel minister among the exiles as Lamentations mourns the city's ruin.
Àwọn ẹsẹ láti sáà yìí
- Ẹkún Jeremiah 3:32nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
- Ẹkún Jeremiah 3:33nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
- Ẹkún Jeremiah 3:34nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
- Ẹkún Jeremiah 3:35nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
- Ẹkún Jeremiah 3:36nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
- Ẹkún Jeremiah 3:37nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
- Ẹkún Jeremiah 3:38nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
- Ẹkún Jeremiah 3:39nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
- Ẹkún Jeremiah 3:40nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
- Ẹkún Jeremiah 3:41nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
- Ẹkún Jeremiah 3:42nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
“Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
- Ẹkún Jeremiah 3:43nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
“Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
- Ẹkún Jeremiah 3:44nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
- Ẹkún Jeremiah 3:45nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
- Ẹkún Jeremiah 3:46nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
“Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
- Ẹkún Jeremiah 3:47nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
- Ẹkún Jeremiah 3:48nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
- Ẹkún Jeremiah 3:49nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
- Ẹkún Jeremiah 3:50nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
- Ẹkún Jeremiah 3:51nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
- Ẹkún Jeremiah 3:52nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
- Ẹkún Jeremiah 3:53nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
- Ẹkún Jeremiah 3:54nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
- Ẹkún Jeremiah 3:55nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
- Ẹkún Jeremiah 3:56nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”