Fò sí àkóónú

circa 605–538 BC

The Babylonian Exile

Jerusalem falls and the temple burns; Ezekiel and Daniel minister among the exiles as Lamentations mourns the city's ruin.

1,784 ẹsẹ · 3 ìwé tí a bo

Àwọn ẹsẹ láti sáà yìí

Sẹ́ nípa ìwé
  1. Ẹkún Jeremiah 3:57nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”

  2. Ẹkún Jeremiah 3:58nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.

  3. Ẹkún Jeremiah 3:59nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!

  4. Ẹkún Jeremiah 3:60nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.

  5. Ẹkún Jeremiah 3:61nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,

  6. Ẹkún Jeremiah 3:62nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.

  7. Ẹkún Jeremiah 3:63nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.

  8. Ẹkún Jeremiah 3:64nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.

  9. Ẹkún Jeremiah 3:65nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.

  10. Ẹkún Jeremiah 3:66nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.

  11. Ẹkún Jeremiah 4:1nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    Báwo ni wúrà ṣe sọ ògo dídán rẹ̀ nù, wúrà dídára di àìdán! Òkúta ibi mímọ́ wá túká sí oríta gbogbo òpópó.

  12. Ẹkún Jeremiah 4:2nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    Báwo ni àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Sioni tí ó ṣe iyebíye, tí wọ́n fi wúrà dídára ṣe wá dàbí ìkòkò amọ̀ lásán iṣẹ́ ọwọ́ amọ̀kòkò!

  13. Ẹkún Jeremiah 4:3nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    Àwọn ajáko pèsè ọmú wọn fún ìtọ́jú àwọn ọmọ wọn, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi wá láì lọ́kàn bí ògòǹgò ní aginjù.

  14. Ẹkún Jeremiah 4:4nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    Nítorí òǹgbẹ, ahọ́n àwọn ọmọ ọwọ́ lẹ̀ mọ́ òkè ẹnu wọn; àwọn ọmọdé bẹ̀bẹ̀ fún oúnjẹ, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó fi fún wọn.

  15. Ẹkún Jeremiah 4:5nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    Àwọn tí ó ń jẹ ohun dáradára di òtòṣì ní òpópó. Àwọn tí a fi aṣọ dáradára wọ̀ ni wọ́n sùn ní orí òkìtì eérú.

  16. Ẹkún Jeremiah 4:6nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    Ìjìyà àwọn ènìyàn mi tóbi ju ti Sodomu lọ, tí a sí ní ipò ní òjijì láìsí ọwọ́ láti ràn án lọ́wọ́.

  17. Ẹkún Jeremiah 4:7nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    Ọmọ ọba ọkùnrin wọn mọ́ ju òjò-dídì, wọ́n sì funfun ju wàrà lọ wọ́n ni ìtọ́jú bí iyùn pupa, ìrísí wọn dàbí safire.

  18. Ẹkún Jeremiah 4:8nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    Ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n dúdú ju èédú; wọn kò sì dá wọn mọ̀ ní òpópó. Ara wọn hun mọ́ egungun; ó sì gbẹ bí igi gbígbẹ.

  19. Ẹkún Jeremiah 4:9nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    Àwọn tí ó kù nípasẹ̀ idà sàn ju àwọn tí ìyàn pa; tí ó wọ àkísà ebi, tí ó ń ṣòfò fún àìní oúnjẹ láti inú pápá.

  20. Ẹkún Jeremiah 4:10nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    Pẹ̀lú ọwọ́ àwọn obìnrin aláàánú ni wọ́n ṣe ọmọ wọn jẹ tí ó di oúnjẹ fún wọn nígbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run.

  21. Ẹkún Jeremiah 4:11nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    Olúwa ti fi ihò kíkún fún ìbínú rẹ̀; ó sì tú ìbínú gbígbóná rẹ̀ jáde. Ó da iná ní Sioni tí ó jó ìpìlẹ̀ rẹ̀ run.

  22. Ẹkún Jeremiah 4:12nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    Àwọn ọba ayé kò gbàgbọ́, tàbí àwọn ènìyàn ayé, wí pé àwọn ọ̀tá àti aninilára le wọ odi ìlú Jerusalẹmu.

  23. Ẹkún Jeremiah 4:13nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    Èyí ṣẹlẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn wòlíì àti àìṣedéédéé àwọn olórí àlùfáà, tí ó ta ẹ̀jẹ̀ àwọn olódodo sílẹ̀ láàrín rẹ̀.

  24. Ẹkún Jeremiah 4:14nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    Nísinsin yìí wọ́n ń rìn kiri ní òpópó bí ọkùnrin tí ó fọ́jú. Ẹ̀jẹ̀ ara wọn sọ wọ́n di àbàwọ́n tí kò sẹ́ni tó láyà láti fọwọ́ kan aṣọ wọn.

  25. Ẹkún Jeremiah 4:15nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi

    “Lọ kúrò! Ẹ̀yin di aláìmọ́!” ni àwọn ènìyàn ń kígbe sí wọn. “Ẹ lọ! Ẹ lọ! Ẹ má ṣe fọwọ́ kàn wá!” Àwọn ènìyàn láàrín orílẹ̀-èdè wí pé, “Wọn kì yóò tẹ̀dó síbí mọ́.”