- English
- King James KJV
- Complete Jewish CJB
- World English WEBM
- Berean Standard BSB
- American Standard ASV
- Geneva GNV
- Young's Literal YLT
- Douay-Rheims DRC
- International
- Shqip ALB
- العربية SVD
- বাংলা BN-IRV
- မြန်မာ Judson
- 简体文 CUV-S
- 繁體中文 CUV-T
- Čeština BKR
- Nederlands STVE
- Français LSG
- Deutsch SCH
- Ελληνικά Vamvas
- ગુજરાતી GU-IRV
- Hausa HCB
- עברית Hebrew
- हिन्दी HCV
- Magyar KAROLI
- Bahasa Indonesia INDO-TB
- Italiano Diodati
- 日本語 Kougo
- 한국어 Korean
- മലയാളം MAL
- मराठी MRCV
- Norsk DNB
- فارسی OPV
- Polski BG
- Português Almeida
- Română Cornilescu
- Русский Synodal
- Español RVG
- Kiswahili Neno
- Svenska SV1917
- Tagalog TAG-ADB
- தமிழ் TCV
- తెలుగు TSA
- ภาษาไทย THAI-KJV
- Українська Ohienko
- Tiếng Việt CADMAN
- Yorùbá YCB
circa 605–538 BC
The Babylonian Exile
Jerusalem falls and the temple burns; Ezekiel and Daniel minister among the exiles as Lamentations mourns the city's ruin.
Àwọn ẹsẹ láti sáà yìí
- Ẹkún Jeremiah 3:7nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
- Ẹkún Jeremiah 3:8nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
- Ẹkún Jeremiah 3:9nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
- Ẹkún Jeremiah 3:10nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
- Ẹkún Jeremiah 3:11nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
- Ẹkún Jeremiah 3:12nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
- Ẹkún Jeremiah 3:13nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
- Ẹkún Jeremiah 3:14nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
- Ẹkún Jeremiah 3:15nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
- Ẹkún Jeremiah 3:16nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
- Ẹkún Jeremiah 3:17nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
- Ẹkún Jeremiah 3:18nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
- Ẹkún Jeremiah 3:19nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
- Ẹkún Jeremiah 3:20nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
- Ẹkún Jeremiah 3:21nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
- Ẹkún Jeremiah 3:22nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
- Ẹkún Jeremiah 3:23nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
- Ẹkún Jeremiah 3:24nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
- Ẹkún Jeremiah 3:25nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
- Ẹkún Jeremiah 3:26nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
- Ẹkún Jeremiah 3:27nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
- Ẹkún Jeremiah 3:28nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
- Ẹkún Jeremiah 3:29nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
- Ẹkún Jeremiah 3:30nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
- Ẹkún Jeremiah 3:31nǹkan bí 588 ṣáájú Kristi
Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.