- English
- King James KJV
- Complete Jewish CJB
- World English WEBM
- Berean Standard BSB
- American Standard ASV
- Geneva GNV
- Young's Literal YLT
- Douay-Rheims DRC
- International
- Shqip ALB
- العربية SVD
- বাংলা BN-IRV
- မြန်မာ Judson
- 简体文 CUV-S
- 繁體中文 CUV-T
- Čeština BKR
- Nederlands STVE
- Français LSG
- Deutsch SCH
- Ελληνικά Vamvas
- ગુજરાતી GU-IRV
- Hausa HCB
- עברית Hebrew
- हिन्दी HCV
- Magyar KAROLI
- Bahasa Indonesia INDO-TB
- Italiano Diodati
- 日本語 Kougo
- 한국어 Korean
- മലയാളം MAL
- मराठी MRCV
- Norsk DNB
- فارسی OPV
- Polski BG
- Português Almeida
- Română Cornilescu
- Русский Synodal
- Español RVG
- Kiswahili Neno
- Svenska SV1917
- Tagalog TAG-ADB
- தமிழ் TCV
- తెలుగు TSA
- ภาษาไทย THAI-KJV
- Українська Ohienko
- Tiếng Việt CADMAN
- Yorùbá YCB
Creation Era
The Tower of Babel
Scattered nations and confused languages mark the beginning of the diversity of peoples across the earth.
Àwọn ẹsẹ láti sáà yìí
- Gẹnẹsisi 10:26nǹkan bí 2247 ṣáájú Kristi
Joktani sì bí Almodadi, Ṣelefi, Hasarmafeti, Jera.
- Gẹnẹsisi 10:27nǹkan bí 2247 ṣáájú Kristi
Hadoramu, Usali, Dikla,
- Gẹnẹsisi 10:28nǹkan bí 2207 ṣáájú Kristi
Obali, Abimaeli, Ṣeba.
- Gẹnẹsisi 10:29nǹkan bí 2207 ṣáájú Kristi
Ofiri, Hafila àti Jobabu. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Joktani.
- Gẹnẹsisi 10:30nǹkan bí 2207 ṣáájú Kristi
Agbègbè ibi tí wọn ń gbé bẹ̀rẹ̀ láti Meṣa títí dé Sefari, ní àwọn ilẹ̀ tó kún fún òkè ní ìlà-oòrùn.
- Gẹnẹsisi 10:31nǹkan bí 2207 ṣáájú Kristi
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Ṣemu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, ní èdè wọn, ní ilẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.
- Gẹnẹsisi 10:32nǹkan bí 2207 ṣáájú Kristi
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Noa gẹ́gẹ́ bí ìran wọn, ní orílẹ̀-èdè wọn. Ní ipasẹ̀ wọn ni àwọn ènìyàn ti tàn ká ilẹ̀ ayé lẹ́yìn ìkún omi.
- Gẹnẹsisi 11:1nǹkan bí 2247 ṣáájú Kristi
Lẹ́yìn náà, gbogbo àgbáyé sì ń sọ èdè kan ṣoṣo.
- Gẹnẹsisi 11:2nǹkan bí 2247 ṣáájú Kristi
Bí àwọn ènìyàn ṣe ń tẹ̀síwájú lọ sí ìhà ìlà-oòrùn, wọ́n rí pẹ̀tẹ́lẹ̀ kan ní ilẹ̀ Ṣinari, wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
- Gẹnẹsisi 11:3nǹkan bí 2247 ṣáájú Kristi
Wọ́n sì wí fún ara wọn pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a mọ bíríkì kí a sì sún wọ́n jìnà.” Bíríkì ni wọ́n ń lò ní ipò òkúta, àti ọ̀dà ilẹ̀ tí wọn ń lò láti mú wọn papọ̀ dípò ẹfun (òkúta láìmù tí wọ́n fi ń ṣe símẹ́ńtì àti omi).
- Gẹnẹsisi 11:4nǹkan bí 2247 ṣáájú Kristi
Nígbà náà ni wọ́n wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a tẹ ìlú kan dó fún ara wa, kí a sì kọ́ ilé ìṣọ́ kan tí yóò kan ọ̀run, kí a ba à lè ní orúkọ, kí a má sì tú káàkiri sórí gbogbo ilẹ̀ ayé.”
- Gẹnẹsisi 11:5nǹkan bí 2247 ṣáájú Kristi
Ṣùgbọ́n, Olúwa sọ̀kalẹ̀ láti wo ìlú àti ilé ìṣọ́ tí àwọn ènìyàn náà ń kọ́.
- Gẹnẹsisi 11:6nǹkan bí 2247 ṣáájú Kristi
Olúwa wí pé, “Bí àwọn ènìyàn bá ń jẹ́ ọ̀kan àti èdè kan tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe iṣẹ́ yìí, kò sí ohun tí wọ́n gbèrò tí wọn kò ní le ṣe yọrí.
- Gẹnẹsisi 11:7nǹkan bí 2247 ṣáájú Kristi
Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a sọ̀kalẹ̀ lọ, kí a da èdè wọn rú kí èdè wọn má ba à yé ara wọn mọ́.”
- Gẹnẹsisi 11:8nǹkan bí 2247 ṣáájú Kristi
Olúwa sì tú wọn ká sórí ilẹ̀ gbogbo, wọ́n sì ṣíwọ́ ìlú náà tí wọn ń tẹ̀dó.
- Gẹnẹsisi 11:9nǹkan bí 2247 ṣáájú Kristi
Ìdí èyí ni a fi pè é ní Babeli nítorí ní ibẹ̀ ni Olúwa ti da èdè gbogbo ayé rú. Olúwa tí sì tú àwọn ènìyàn ká sí gbogbo orí ilẹ̀ ayé.
- Gẹnẹsisi 11:10nǹkan bí 2346 ṣáájú Kristi
Wọ̀nyí ni ìran Ṣemu. Ọdún méjì lẹ́yìn ìkún omi, tí Ṣemu pé ọgọ́rùn-ún ọdún ni ó bí Arfakṣadi.
- Gẹnẹsisi 11:11nǹkan bí 1846 ṣáájú Kristi
Lẹ́yìn tí ó bí Arfakṣadi, Ṣemu tún wà láààyè fún ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ọdún (500), ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
- Gẹnẹsisi 11:12nǹkan bí 2311 ṣáájú Kristi
Nígbà tí Arfakṣadi pé ọdún márùndínlógójì ni ó bí Ṣela.
- Gẹnẹsisi 11:13nǹkan bí 1908 ṣáájú Kristi
Arfakṣadi sì wà láààyè fún ọdún mẹ́tàlénírinwó (403) lẹ́yìn tí ó bí Ṣela, ó sì bí àwọn ọmọbìnrin àti àwọn ọmọkùnrin mìíràn.
- Gẹnẹsisi 11:14nǹkan bí 2281 ṣáájú Kristi
Nígbà tí Ṣela pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Eberi.
- Gẹnẹsisi 11:15nǹkan bí 1878 ṣáájú Kristi
Ṣela sì wà láààyè fún ọdún mẹ́tàlénírinwó (403) lẹ́yìn tí ó bí Eberi tán, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
- Gẹnẹsisi 11:16nǹkan bí 2247 ṣáájú Kristi
Eberi sì jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n, ó sì bí Pelegi.
- Gẹnẹsisi 11:17nǹkan bí 1817 ṣáájú Kristi
Eberi sì wà láààyè fún irinwó ọdún ó lé ọgbọ̀n (430) lẹ́yìn tí ó bí Pelegi, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
- Gẹnẹsisi 11:18nǹkan bí 2217 ṣáájú Kristi
Nígbà tí Pelegi pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Reu.