Fò sí àkóónú

circa 1010–970 BC

The Reign of David

David unites the tribes, conquers Jerusalem, and establishes Israel's golden age—even through deep personal failure.

1,230 ẹsẹ · 2 ìwé tí a bo

Àwọn ẹsẹ láti sáà yìí

Sẹ́ nípa ìwé
  1. 1 Kronika 11:17nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Dafidi sí pòǹgbẹ fún omi ó sì wí pé, “Háà, ẹnìkan yóò ha bu omi láti inú kànga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-bodè Bẹtilẹhẹmu fún un mu?”

  2. 1 Kronika 11:18nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Bẹ́ẹ̀ ni àwọn mẹ́ta náà sì là láti ogun ará Filistini, ó sì fa omi jáde láti inú kànga ní ẹ̀gbẹ́ ẹnu-bodè Bẹtilẹhẹmu ó sì gbé padà tọ Dafidi wá. Ṣùgbọ́n ó kọ̀ láti mu ú: dípò, ó sì tú jáde níwájú Olúwa.

  3. 1 Kronika 11:19nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    “Kí Ọlọ́run má jẹ́ kí èmi ó má ṣe ṣe èyí!” ó wí pé. “Ṣé kí èmi kí ó mú ẹ̀jẹ̀ ọkùnrin yí ẹni tí ó fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu?” Nítorí wọ́n fi ẹ̀mí wọn wéwu láti mú padà wá, Dafidi kò ní mu ú. Nǹkan wọ̀nyí ni àwọn akọni mẹ́ta ọkùnrin náà ṣe ohun ìyanu ńlá.

  4. 1 Kronika 11:20nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Abiṣai arákùnrin Joabu ìjòyè àwọn mẹ́ta. Ó sì gbé ọ̀kọ̀ rẹ̀ sókè lórí àwọn ọ̀ọ́dúnrún (300) àwọn ènìyàn, àwọn ẹni tí ó pa, bẹ́ẹ̀ ni ó sì di olókìkí gẹ́gẹ́ bí àwọn mẹ́ta.

  5. 1 Kronika 11:21nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Ó sì gba ìlọ́po ọlá lórí àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta ó sì di olórí wọn, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a kò ka kún ara wọn.

  6. 1 Kronika 11:22nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Benaiah ọmọ Jehoiada ó sì jẹ́ akọni oníjà láti Kabṣeeli, ẹni tí ó ṣe iṣẹ́ agbára ńlá. Ó sì pa àwọn ọmọ Arieli méjì ti Moabu, ó sì tún sọ̀kalẹ̀ lọ sí inú ihò lákokò yìnyín dídì, ó sì pa kìnnìún kan

  7. 1 Kronika 11:23nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Ó sì pa ara Ejibiti ẹni tí ó ga ní ìwọ̀n ẹsẹ̀ méje àti ààbọ̀ ṣùgbọ́n àwọn ará Ejibiti wọn ní ọ̀kọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìdábùú igi ahunṣọ àti ọ̀pá ní ọwọ́ rẹ̀, Benaiah sọ̀kalẹ̀ lórí rẹ̀ pẹ̀lú kùmọ̀. Ó sì gba ọ̀kọ̀ náà láti ọwọ́ ará Ejibiti ó sì pa á pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀.

  8. 1 Kronika 11:24nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Nǹkan wọ̀nyí sì ní ìwà akin Benaiah ọmọ Jehoiada; ohun náà pẹ̀lú sì di olókìkí gẹ́gẹ́ bí àwọn akọni ọkùnrin mẹ́ta.

  9. 1 Kronika 11:25nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Ó sì ní ọlá púpọ̀ ju àwọn ọgbọ̀n lọ, ṣùgbọ́n a kò kà á láàrín àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta. Dafidi sì fi sí ìkáwọ́ àwọn ẹ̀ṣọ́.

  10. 1 Kronika 11:26nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Àwọn akọni ọkùnrin náà nìyí: Asaheli arákùnrin Joabu, Elhanani ọmọ Dodo láti Bẹtilẹhẹmu,

  11. 1 Kronika 11:27nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Ṣamotu ará Harori, Helesi ará Peloni

  12. 1 Kronika 11:28nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Ira ọmọ Ikẹsi láti Tekoa, Abieseri láti Anatoti,

  13. 1 Kronika 11:29nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Sibekai ará Huṣati, láti ará Ahohi

  14. 1 Kronika 11:30nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Maharai ará Netofa, Heledi ọmọ Baanah ará Netofa,

  15. 1 Kronika 11:31nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Itai ọmọ Ribai láti Gibeah ní Benjamini, Benaiah ará Piratoni,

  16. 1 Kronika 11:32nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Hurai láti àfonífojì Gaaṣi, Abieli ará Arbati,

  17. 1 Kronika 11:33nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Asmafeti ará Bahurimu Eliaba ará Ṣaalboni.

  18. 1 Kronika 11:34nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Àwọn ọmọ Haṣemu ará Gisoni Jonatani ọmọ Ṣage ará Harari.

  19. 1 Kronika 11:35nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Ahiamu ọmọ Sakari ará Harari, Elifali ọmọ Uri

  20. 1 Kronika 11:36nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Heferi ará Mekerati, Ahijah ará Peloni,

  21. 1 Kronika 11:37nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Hesro ará Karmeli Naarai ọmọ Esbai,

  22. 1 Kronika 11:38nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Joẹli arákùnrin Natani Mibari ọmọ Hagari,

  23. 1 Kronika 11:39nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Seleki ará Ammoni, Naharai ará Beroti ẹni tí ó jẹ́ ẹni tí n ru ìhámọ́ra Joabu ọmọ Seruiah.

  24. 1 Kronika 11:40nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Ira ará Itri, Garebu ará Itri,

  25. 1 Kronika 11:41nǹkan bí 1055 ṣáájú Kristi

    Uriah ará Hiti Sabadi ọmọ Ahlai.