Fò sí àkóónú

circa AD 48–96

Letters to the Churches

Paul and other apostles write to strengthen, correct, and encourage the scattered churches across the Roman world.

2,767 ẹsẹ · 21 ìwé tí a bo

Àwọn ẹsẹ láti sáà yìí

Sẹ́ nípa ìwé
  1. 1 Kọrinti 14:28nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Ṣùgbọ́n bí kò bá sí ògbufọ̀, kí ó pa ẹnu rẹ̀ mọ́ nínú ìjọ; sì jẹ́ kí ó máa bá ara rẹ̀ àti Ọlọ́run sọ̀rọ̀.

  2. 1 Kọrinti 14:29nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Jẹ́ kí àwọn wòlíì méjì tàbí mẹ́ta sọ̀rọ̀, ki àwọn ìyókù sì wòye ìtumọ̀ ohun tí a sọ.

  3. 1 Kọrinti 14:30nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Bí a bá sì fi ohunkóhun hàn ẹni tí ó jókòó níbẹ̀, jẹ́ kí ẹni tí ó kọ́ sọ̀rọ̀ ṣáájú dákẹ́.

  4. 1 Kọrinti 14:31nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Nítorí gbogbo yín lè sọtẹ́lẹ̀ ni ọ̀kọ̀ọ̀kan, kí gbogbo yín lè kọ́ ẹ̀kọ́, kí a lè tu gbogbo yín nínú.

  5. 1 Kọrinti 14:32nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Ẹ̀mí àwọn wòlíì a sí máa tẹríba fún àwọn wòlíì.

  6. 1 Kọrinti 14:33nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Nítorí Ọlọ́run kì í ṣe Ọlọ́run ohun rúdurùdu, ṣùgbọ́n ti àlàáfíà. Gẹ́gẹ́ bí ó ti jẹ́ nínú gbogbo ìjọ ènìyàn mímọ́.

  7. 1 Kọrinti 14:34nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Jẹ́ ki àwọn obìnrin yín dákẹ́ nínú ìjọ, nítorí a kò fi fún wọn láti sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n jẹ́ kí wọn wà lábẹ́ ìtẹríba, gẹ́gẹ́ bí òfin pẹ̀lú ti wí.

  8. 1 Kọrinti 14:35nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Bí wọ́n bá sì fẹ́ mọ̀ nípa ohunkóhun, kí wọn béèrè lọ́wọ́ ọkọ wọn ní ilé; nítorí ohun ìtìjú ni fún àwọn obìnrin láti máa sọ̀rọ̀ nínú ìjọ.

  9. 1 Kọrinti 14:36nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Kín ni? Ṣe lọ́dọ̀ yín ní ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ti jáde ni, tàbí ẹ̀yin nìkan ni o tọ̀ wá?

  10. 1 Kọrinti 14:37nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Bí ẹnikẹ́ni bá ró ará rẹ̀ pé òun jẹ́ wòlíì, tàbí òun jẹ́ ẹni tí ó ní ẹ̀bùn ẹ̀mí, jẹ́ kí nǹkan wọ̀nyí ti mo kọ sí yin yé e dájú pé òfin Olúwa ni wọ́n.

  11. 1 Kọrinti 14:38nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Ṣùgbọ́n bí ẹnìkan bá fi ojú fo èyí dá, òun fúnra rẹ̀ ní a ó fi ojú fò dá.

  12. 1 Kọrinti 14:39nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Nítorí náà ará, ẹ máa fi ìtara ṣàfẹ́rí láti sọtẹ́lẹ̀, kí ẹ má sì ṣe dánilẹ́kun láti fi èdè fọ̀.

  13. 1 Kọrinti 14:40nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Ẹ máa ṣe ohun gbogbo tẹ̀yẹtẹ̀yẹ àti lẹ́sẹẹsẹ.

  14. 1 Kọrinti 15:1nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Ǹjẹ́ ará, èmi ń sọ ìyìnrere náà dí mí mọ̀ fún un yín, tí mo ti wàásù fún un yín, èyí tí ẹ̀yin pẹ̀lú ti gbá, nínú èyí tí ẹ̀yin sì dúró.

  15. 1 Kọrinti 15:2nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Nípasẹ̀ ìyìnrere yìí ni a fi ń gbà yín là pẹ̀lú, bí ẹ̀yin bá di ọ̀rọ̀ ti mo ti wàásù fún yín mú ṣinṣin. Bí bẹ́ẹ̀ kọ̀, ẹ̀yin kàn gbàgbọ́ lásán.

  16. 1 Kọrinti 15:3nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Nítorí èyí tí mo rí gbà ṣáájú ohun gbogbo ní èmi pẹ̀lú ti fi lé e yín lọ́wọ́, bí Kristi ti kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bí ìwé mímọ́ tí wí.

  17. 1 Kọrinti 15:4nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Àti pé a sìnkú rẹ̀, àti pé ó jíǹde ní ọjọ́ kẹta gẹ́gẹ́ bí Ìwé Mímọ́ tí wí;

  18. 1 Kọrinti 15:5nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    àti pé ó farahàn Peteru, lẹ́yìn èyí, àwọn méjìlá.

  19. 1 Kọrinti 15:6nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Lẹ́yìn èyí, ó farahàn àwọn ará tí o jú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta (500) lọ lẹ́ẹ̀kan náà; ọ̀pọ̀ nínú wọn wà títí fi di ìsinsin yìí, ṣùgbọ́n àwọn díẹ̀ ti sùn.

  20. 1 Kọrinti 15:7nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Lẹ́yìn èyí ni ó farahan Jakọbu; lẹ́yìn náà fún gbogbo àwọn aposteli.

  21. 1 Kọrinti 15:8nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Àti níkẹyìn gbogbo wọn ó farahàn mí pẹ̀lú, bí ẹni tí a bí ṣáájú àkókò rẹ̀.

  22. 1 Kọrinti 15:9nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Nítorí èmi ni ẹni tí ó kéré jùlọ nínú àwọn aposteli, èmi ẹni tí kò yẹ láti pè ní aposteli, nítorí tí mo ṣe inúnibíni sí ìjọ ènìyàn Ọlọ́run.

  23. 1 Kọrinti 15:10nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Ṣùgbọ́n nípa oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run mo rí bí mo ti rí: oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ tí a fi fún mi kò sì jẹ́ asán; ṣùgbọ́n mó ṣiṣẹ́ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ jú gbogbo wọn lọ, ṣùgbọ́n kì í ṣe èmi, bí kò ṣe oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run tí ó wà pẹ̀lú mi.

  24. 1 Kọrinti 15:11nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Nítorí náà ìbá à ṣe èmí tàbí àwọn ni, èyí ní àwa wàásù, èyí ní ẹ̀yin sì gbàgbọ́.

  25. 1 Kọrinti 15:12nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Ǹjẹ́ bí a bá wàásù Kristi pé ó tí jíǹde kúrò nínú òkú, èéha tí ṣe tí àwọn mìíràn nínú yín fi wí pé, àjíǹde òkú kò sí.