Fò sí àkóónú

circa AD 48–96

Letters to the Churches

Paul and other apostles write to strengthen, correct, and encourage the scattered churches across the Roman world.

2,767 ẹsẹ · 21 ìwé tí a bo

Àwọn ẹsẹ láti sáà yìí

Sẹ́ nípa ìwé
  1. 1 Kọrinti 15:13nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Ṣùgbọ́n bí àjíǹde òkú kò sí, ǹjẹ́ Kristi kò jíǹde.

  2. 1 Kọrinti 15:14nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Bí Kristi kò bá sì jíǹde, ǹjẹ́ asán ni ìwàásù wà, asán sì ni ìgbàgbọ́ yín pẹ̀lú.

  3. 1 Kọrinti 15:15nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Ṣùgbọ́n jù bẹ́ẹ̀ lọ, a mú wa ni ẹlẹ́rìí èké fún Ọlọ́run; nítorí ti àwa jẹ́rìí Ọlọ́run pé ó jí Kristi dìde kúrò nínú òkú: ẹni tí òun kò jí dìde bí ó bá ṣe pé àwọn òkú kò jíǹde?

  4. 1 Kọrinti 15:16nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Nítorí pé bi á kò bá jí àwọn òkú dìde, ǹjẹ́ a kò jí Kristi dìde,

  5. 1 Kọrinti 15:17nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    bí a kò bá sì jí Kristi dìde, asán ní ìgbàgbọ́ yín; ẹ̀yin wà nínú ẹ̀ṣẹ̀ yín síbẹ̀.

  6. 1 Kọrinti 15:18nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Ǹjẹ́ àwọn pẹ̀lú tí ó sùn nínú Kristi ṣègbé.

  7. 1 Kọrinti 15:19nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Bí ó bá ṣe pé kìkì ayé yìí nìkan ní àwa ní ìrètí nínú Kristi, àwa jásí òtòṣì jùlọ nínú gbogbo ènìyàn.

  8. 1 Kọrinti 15:20nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Ǹjẹ́ nísinsin yìí Kristi tí jíǹde kúrò nínú òkú, ó sì dí àkọ́bí nínú àwọn tí ó sùn.

  9. 1 Kọrinti 15:21nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Nítorí ìgbà tí ó jẹ́ pé nípa ènìyàn ní ikú ti wá, nípa ènìyàn ní àjíǹde òkú sì ti wá pẹ̀lú.

  10. 1 Kọrinti 15:22nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Nítorí bí gbogbo ènìyàn ti kú nínú Adamu, bẹ́ẹ̀ ní a ó sì sọ gbogbo ènìyàn dí alààyè nínú Kristi.

  11. 1 Kọrinti 15:23nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Ṣùgbọ́n olúkúlùkù ènìyàn ní ipá tirẹ̀: Kristi àkọ́bí; lẹ́yìn èyí àwọn tí ó jẹ́ tí Kristi ni wíwá rẹ̀.

  12. 1 Kọrinti 15:24nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Nígbà náà ni òpin yóò dé, nígbà tí ó bá ti fi ìjọba fún Ọlọ́run Baba, nígbà tí ó bá pa gbogbo àṣẹ àti gbogbo ọlá àti agbára run.

  13. 1 Kọrinti 15:25nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Nítorí ti òun gbọdọ̀ ti jẹ ọba kí òun to fi gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ̀ sí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.

  14. 1 Kọrinti 15:26nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Ikú ní ọ̀tá ìkẹyìn tí a ó parun.

  15. 1 Kọrinti 15:27nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    “Nítorí ó ti fi ohun gbogbo sábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.” Ṣùgbọ́n nígbà tí ó wí pé, “Ohun gbogbo ni á fi sí abẹ́ rẹ̀,” o dájú pé Ọlọ́run nìkan ṣoṣo ní kò sí ní abẹ́ rẹ̀, Òun ní ó fi ohun gbogbo sí abẹ́ àkóso Kristi.

  16. 1 Kọrinti 15:28nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Nígbà tí a bá sì fi ohun gbogbo sí abẹ́ rẹ̀ tán, nígbà náà ni á ó fi ọmọ tìkára rẹ̀ pẹ̀lú sábẹ́ ẹni tí ó fi ohun gbogbo sí abẹ́ rẹ̀, kí Ọlọ́run lè jásí ohun gbogbo nínú ohun gbogbo.

  17. 1 Kọrinti 15:29nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Ní báyìí, bí kò bá sí àjíǹde, kín ní ète àwọn ènìyàn tí wọn ń tẹ bọ omi nítorí òkú? Bí àwọn òkú kò bá jíǹde rárá, nítorí kín ni a ṣe ń bamitiisi wọn nítorí wọn?

  18. 1 Kọrinti 15:30nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Nítorí kín ní àwa sì ṣe ń bẹ nínú ewu ni wákàtí gbogbo?

  19. 1 Kọrinti 15:31nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Mo sọ nípa ayọ̀ tí mo ní lórí yín nínú Kristi Jesu Olúwa wá pé, èmi ń kú lójoojúmọ́.

  20. 1 Kọrinti 15:32nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Kí a wí bí ènìyàn, bí mo bá ẹranko jà ní Efesu, àǹfààní kín ni ó jẹ́ fún mi? Bí àwọn òkú kò bá jíǹde, “Ẹ jẹ́ kí a máa jẹ, kí á máa mú; nítorí ní ọlá ni àwa ó kú.”

  21. 1 Kọrinti 15:33nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Kí a má tàn yín jẹ́, “Ẹgbẹ́ búburú bá ìwà rere jẹ́.”

  22. 1 Kọrinti 15:34nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Ẹ jí ìjí òdodo, kí ẹ má sì dẹ́ṣẹ̀; nítorí àwọn ẹlòmíràn kò ni imọ̀ Ọlọ́run, mo sọ èyí kí ojú ba à lè tiyín.

  23. 1 Kọrinti 15:35nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Ṣùgbọ́n ẹnìkan yóò wí pé, “Báwo ni àwọn òkú yóò ṣe jíǹde? Irú ara wó ni wọn ó padà sí?”

  24. 1 Kọrinti 15:36nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    Ìwọ aláìmòye, ohun tí ìwọ fúnrúgbìn kì í yè bí kò ṣe pé ó ba kú,

  25. 1 Kọrinti 15:37nǹkan bí 59 lẹ́yìn Kristi

    àti èyí tí ìwọ fúnrúgbìn, kì í ṣe ara tí ń bọ̀ ni ìwọ fúnrúgbìn, ṣùgbọ́n èso lásán ni, ìbá à ṣe alikama, tàbí irú mìíràn.