Fò sí àkóónú

circa 1900–1700 BC

Jacob, Joseph & Egypt

Jacob wrestles with God and becomes Israel; Joseph is sold into slavery yet rises to save the world from famine.

840 ẹsẹ · 1 ìwé tí a bo

Àwọn ẹsẹ láti sáà yìí

  1. Gẹnẹsisi 36:28nǹkan bí 1756 ṣáájú Kristi

    Àwọn ọmọ Diṣani ni: Usi àti Arani.

  2. Gẹnẹsisi 36:29nǹkan bí 1756 ṣáájú Kristi

    Àwọn wọ̀nyí ni olórí ìdílé Hori: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,

  3. Gẹnẹsisi 36:30nǹkan bí 1756 ṣáájú Kristi

    Diṣoni Eseri, àti Diṣani. Àwọn ni olórí ìdílé àwọn ará Hori gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn ní ilẹ̀ Seiri.

  4. Gẹnẹsisi 36:31nǹkan bí 1756 ṣáájú Kristi

    Àwọn wọ̀nyí ni ọba tí ó jẹ ní Edomu kí ó tó di pé ọba kankan jẹ lórí Israẹli:

  5. Gẹnẹsisi 36:32nǹkan bí 1756 ṣáájú Kristi

    Bela ọmọ Beori jẹ ní Edomu. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Dinhaba.

  6. Gẹnẹsisi 36:33nǹkan bí 1869 ṣáájú Kristi

    Nígbà tí Bela kú, Jobabu ọmọ Sera ti Bosra sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

  7. Gẹnẹsisi 36:34nǹkan bí 1827 ṣáájú Kristi

    Nígbà tí Jobabu kú, Huṣamu láti ilẹ̀ Temani sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

  8. Gẹnẹsisi 36:35nǹkan bí 1785 ṣáájú Kristi

    Nígbà tí Huṣamu kú, Hadadi ọmọ Bedadi tí ó kọlu Midiani ní ìgbẹ́ Moabu, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Afiti.

  9. Gẹnẹsisi 36:36nǹkan bí 1743 ṣáájú Kristi

    Nígbà tí Hadadi sì kú, Samla láti Masreka, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

  10. Gẹnẹsisi 36:37nǹkan bí 1701 ṣáájú Kristi

    Samla sì kú, Saulu ti Rehoboti, létí odò sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

  11. Gẹnẹsisi 36:38nǹkan bí 1659 ṣáájú Kristi

    Nígbà tí Saulu kú, Baali-Hanani ọmọ Akbori jẹ ọba ní ipò rẹ̀.

  12. Gẹnẹsisi 36:39nǹkan bí 1617 ṣáájú Kristi

    Nígbà tí Baali-Hanani ọmọ Akbori kú, Hadadi ni ó jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Pau, orúkọ ìyàwó sì ni Mehetabeeli ọmọbìnrin Matiredi, ọmọbìnrin Mesahabu.

  13. Gẹnẹsisi 36:40nǹkan bí 1617 ṣáájú Kristi

    Àwọn wọ̀nyí ni orúkọ àwọn baálẹ̀ tí ó ti ọ̀dọ̀ Esau jáde wá, ní orúkọ ìdílé wọn, bí ìpínlẹ̀ wọn ti rí: baálẹ̀ Timna, baálẹ̀ Alfa, baálẹ̀ Jeteti.

  14. Gẹnẹsisi 36:41nǹkan bí 1617 ṣáájú Kristi

    Baálẹ̀ Oholibama, baálẹ̀ Ela, baálẹ̀ Pinoni,

  15. Gẹnẹsisi 36:42nǹkan bí 1617 ṣáájú Kristi

    baálẹ̀ Kenasi, baálẹ̀ Temani, baálẹ̀ Mibsari,

  16. Gẹnẹsisi 36:43nǹkan bí 1617 ṣáájú Kristi

    Magdieli, àti Iramu. Àwọn wọ̀nyí ni baálẹ̀ Edomu, gẹ́gẹ́ bí wọn ti tẹ̀dó sí ilẹ̀ tí wọ́n gbà. Èyí ni Esau baba àwọn ará Edomu.

  17. Gẹnẹsisi 37:1nǹkan bí 1728 ṣáájú Kristi

    Jakọbu sì gbé ilẹ̀ Kenaani ní ibi ti baba rẹ̀ ti gbé.

  18. Gẹnẹsisi 37:2nǹkan bí 1728 ṣáájú Kristi

    Èyí ni àwọn ìtàn Jakọbu. Nígbà tí Josẹfu di ọmọ ọdún mẹ́tàdínlógún, ó ń ṣọ́ agbo ẹran pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ̀, àwọn ọmọ Biliha àti Silipa aya baba rẹ̀ Josẹfu sì ń ròyìn àwọn aburú tí wọ́n ń ṣe fún baba wọn.

  19. Gẹnẹsisi 37:3nǹkan bí 1728 ṣáájú Kristi

    Israẹli sì fẹ́ràn Josẹfu ju gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀ tókù lọ, nítorí ní ọjọ́ ogbó rẹ̀ ni ó bí i. O sì dá aṣọ aláràbarà tí ó kún fún onírúurú ọnà lára fún un.

  20. Gẹnẹsisi 37:4nǹkan bí 1728 ṣáájú Kristi

    Nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ rí i pé baba àwọn fẹ́ràn rẹ̀ ju gbogbo wọn lọ, wọ́n kórìíra rẹ̀, wọ́n sì ń fi ẹ̀tanú bá a gbé, kò sì sí àlàáfíà láàrín wọn.

  21. Gẹnẹsisi 37:5nǹkan bí 1728 ṣáájú Kristi

    Josẹfu lá àlá kan, nígbà tí ó sì sọ fún àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n túbọ̀ kórìíra rẹ̀ sí i.

  22. Gẹnẹsisi 37:6nǹkan bí 1728 ṣáájú Kristi

    O wí fún wọn pé, “Ẹ fetí sí àlá tí mo lá,

  23. Gẹnẹsisi 37:7nǹkan bí 1728 ṣáájú Kristi

    sá à wò ó, àwa ń yí ìtí ọkà nínú oko, ó sì ṣe ìtí ọkà tèmi sì dìde dúró ṣánṣán, àwọn ìtí ọkà tiyín sì dúró yí ìtí tèmi ká, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún un.”

  24. Gẹnẹsisi 37:8nǹkan bí 1728 ṣáájú Kristi

    Àwọn arákùnrin rẹ̀ wí fún un pé, “Ìwọ ń gbèrò àti jẹ ọba lé wa lórí bí? Tàbí ìwọ ó ṣe olórí wa nítòótọ́?” Wọn sì túbọ̀ kórìíra rẹ̀ sí i, nítorí àlá rẹ̀ àti nítorí ohun tí ó wí.

  25. Gẹnẹsisi 37:9nǹkan bí 1728 ṣáájú Kristi

    O sì tún lá àlá mìíràn, ó sì tún sọ ọ́ fún àwọn arákùnrin rẹ̀. Ó wí pé, ẹ tẹ́tí sí mi, “Mo tún lá àlá mìíràn, wò ó, oòrùn, òṣùpá àti ìràwọ̀ mọ́kànlá ń foríbalẹ̀ fún mi.”