Fò sí àkóónú

circa 1900–1700 BC

Jacob, Joseph & Egypt

Jacob wrestles with God and becomes Israel; Joseph is sold into slavery yet rises to save the world from famine.

840 ẹsẹ · 1 ìwé tí a bo

Àwọn ẹsẹ láti sáà yìí

  1. Gẹnẹsisi 26:26nǹkan bí 1804 ṣáájú Kristi

    Nígbà náà ni Abimeleki tọ̀ ọ́ wá láti Gerari, àti Ahussati, olùdámọ̀ràn rẹ̀ àti Fikoli, olórí ogun rẹ̀.

  2. Gẹnẹsisi 26:27nǹkan bí 1804 ṣáájú Kristi

    Isaaki sì bi wọ́n léèrè pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin tọ̀ mí wá, níwọ̀n ìgbà tí ẹ̀yin kórìíra mi tí ẹ sì lé mi jáde kúrò lọ́dọ̀ yín?”

  3. Gẹnẹsisi 26:28nǹkan bí 1804 ṣáájú Kristi

    Wọ́n dáhùn pé, “A rí i dájú pé Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, nítorí náà ni a fi rò ó wí pé, ó yẹ kí májẹ̀mú kí o wà láàrín àwa àti ìwọ. Jẹ́ kí a ṣe àdéhùn

  4. Gẹnẹsisi 26:29nǹkan bí 1804 ṣáájú Kristi

    pé ìwọ kì yóò ṣe wá ní ibi, bí àwa pẹ̀lú kò ti ṣe ọ́ ní aburú, tí a sì ń ṣe ọ́ dáradára, tí a sì rán ọ jáde ní àlàáfíà láìṣe ọ́ ní ibi, kíyèsi Olúwa sì ti bùkún fún ọ.”

  5. Gẹnẹsisi 26:30nǹkan bí 1804 ṣáájú Kristi

    Isaaki sì ṣe àsè fún wọn, wọn sì jẹ, wọ́n sì mu.

  6. Gẹnẹsisi 26:31nǹkan bí 1804 ṣáájú Kristi

    Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì wọn búra fún ara wọn. Isaaki sì rán wọn lọ, wọ́n sì lọ ní àlàáfíà.

  7. Gẹnẹsisi 26:32nǹkan bí 1804 ṣáájú Kristi

    Ní ọjọ́ náà gan an ni àwọn ìránṣẹ́ Isaaki wá sọ fún un pé àwọn ti kan omi ní kànga kan tí àwọn gbẹ́.

  8. Gẹnẹsisi 26:33nǹkan bí 1804 ṣáájú Kristi

    Ó sì pe orúkọ kànga náà ní Ṣiba, títí di òní olónìí, orúkọ ìlú náà ni Beerṣeba.

  9. Gẹnẹsisi 26:34nǹkan bí 1796 ṣáájú Kristi

    Nígbà tí Esau pé ọmọ ogójì ọdún ó fẹ́ ọmọbìnrin kan tí a ń pè ní Juditi, ọmọ Beeri, ará Hiti, ó sì tún fẹ́ Basemati, ọmọ Eloni ará Hiti.

  10. Gẹnẹsisi 26:35nǹkan bí 1796 ṣáájú Kristi

    Fífẹ́ tí a fẹ́ àwọn obìnrin wọ̀nyí jẹ́ ìbànújẹ́ fún Isaaki àti Rebeka.

  11. Gẹnẹsisi 27:1nǹkan bí 1760 ṣáájú Kristi

    Nígbà ti Isaaki di arúgbó, ojú rẹ̀ sì ti di bàìbàì tó bẹ́ẹ̀ tí kò le ríran. Ó pe Esau àkọ́bí rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Ọmọ mi.” Esau sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”

  12. Gẹnẹsisi 27:2nǹkan bí 1760 ṣáájú Kristi

    Isaaki sì wí pé, “Nísinsin yìí mo di arúgbó, èmi kò sì mọ ọjọ́ tí èmi yóò kú.

  13. Gẹnẹsisi 27:3nǹkan bí 1760 ṣáájú Kristi

    Nítorí náà, mú ohun èlò ọdẹ rẹ, apó àti ọrún, nísinsin yìí kí o sì lọ pa ẹran wá fún mi nínú igbó.

  14. Gẹnẹsisi 27:4nǹkan bí 1760 ṣáájú Kristi

    Kí o sì ṣe ẹran àdídùn fún mi, irú èyí tí mo fẹ́ràn, kí o gbe wá fún mi kí n jẹ, kí n sì súre fún ọ kí n tó kú.”

  15. Gẹnẹsisi 27:5nǹkan bí 1760 ṣáájú Kristi

    Ṣùgbọ́n Rebeka ń fetí léko gbọ́ nígbà tí Isaaki ń bá Esau ọmọ rẹ̀ sọ̀rọ̀. Nítorí náà, nígbà ti Esau ti ṣe ọdẹ lọ sínú igbó,

  16. Gẹnẹsisi 27:6nǹkan bí 1760 ṣáájú Kristi

    Rebeka sọ fún Jakọbu ọmọ rẹ̀ pé, “Wò ó, mo gbọ́ tí baba rẹ ń wí fún Esau ẹ̀gbọ́n rẹ pé,

  17. Gẹnẹsisi 27:7nǹkan bí 1760 ṣáájú Kristi

    ‘Pa ẹran fún mi wá, kí o sì ṣe oúnjẹ àdídùn fún mi láti jẹ, kí n ba à le súre fún ọ níwájú Olúwa kí èmi tó kú.’

  18. Gẹnẹsisi 27:8nǹkan bí 1760 ṣáájú Kristi

    Nísinsin yìí ọmọ mi, gbọ́ tèmi, kí o sì ṣe ohun tí èmi yóò wí fún ọ.

  19. Gẹnẹsisi 27:9nǹkan bí 1760 ṣáájú Kristi

    Lọ sínú agbo ẹran, kí o sì mú ọmọ ewúrẹ́ méjì, kí ó lè ṣe oúnjẹ àdídùn fún baba rẹ, irú èyí tí ó fẹ́ràn dáradára.

  20. Gẹnẹsisi 27:10nǹkan bí 1760 ṣáájú Kristi

    Ìwọ yóò sì gbé e tọ baba rẹ lọ, kí òun ba à lè jẹ ẹ́, kí ó sì súre fún ọ, kí ó tó kú.”

  21. Gẹnẹsisi 27:11nǹkan bí 1760 ṣáájú Kristi

    Jakọbu sì wí fún Rebeka ìyá rẹ̀ pé, “Ṣùgbọ́n Esau ẹ̀gbọ́n mi jẹ́ ènìyàn onírun lára, bẹ́ẹ̀ alára ọ̀bọ̀rọ́ sì ni èmi,

  22. Gẹnẹsisi 27:12nǹkan bí 1760 ṣáájú Kristi

    bí baba mi bá fọwọ́ kàn mi ń kọ́? Èmi yóò jọ ẹlẹ́tàn lójú rẹ̀, dípò kí ó súre fún mi, èmi yóò sì mú ègún wá sórí ara mi.”

  23. Gẹnẹsisi 27:13nǹkan bí 1760 ṣáájú Kristi

    Ìyá rẹ̀ wá wí fun un pé, “Ọmọ mi jẹ́ kí ègún náà wá sórí mi, sá à ṣe ohun tí mo wí, kí o sì mú wọn wá fún mi.”

  24. Gẹnẹsisi 27:14nǹkan bí 1760 ṣáájú Kristi

    Jakọbu sì ṣe ohun gbogbo tí ìyá rẹ̀ wí fun un, Rebeka sì ṣe oúnjẹ àdídùn náà, irú èyí tí Isaaki fẹ́ràn.

  25. Gẹnẹsisi 27:15nǹkan bí 1760 ṣáájú Kristi

    Nígbà náà ni Rebeka mú èyí tí ó dára jù nínú aṣọ Esau ọmọ rẹ̀ àgbà tí ó wà nínú ilé Rebeka, ó sì fi wọ Jakọbu ọmọ rẹ̀ àbúrò.