Fò sí àkóónú

circa 1010–970 BC

The Reign of David

David unites the tribes, conquers Jerusalem, and establishes Israel's golden age—even through deep personal failure.

1,230 ẹsẹ · 2 ìwé tí a bo

Àwọn ẹsẹ láti sáà yìí

Sẹ́ nípa ìwé
  1. 2 Samuẹli 22:21nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    “Olúwa sán án fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi; ó sì san án fún mi gẹ́gẹ́ bí mímọ́ ọwọ́ mi.

  2. 2 Samuẹli 22:22nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    Nítorí pé èmi pa ọ̀nà Olúwa mọ́, èmi kò sì fi ìwà búburú yapa kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run mi.

  3. 2 Samuẹli 22:23nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    Nítorí pé gbogbo ìdájọ́ rẹ̀ ni ó wà níwájú mi; àti ní ti òfin rẹ̀, èmi kò sì yapa kúrò nínú wọn.

  4. 2 Samuẹli 22:24nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    Èmi sì wà nínú ìwà títọ́ sí í, èmi sì pa ara mi mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ mi.

  5. 2 Samuẹli 22:25nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    Olúwa sì san fún mi gẹ́gẹ́ bí òdodo mi, gẹ́gẹ́ bí ìwà mímọ́ mi níwájú rẹ̀.

  6. 2 Samuẹli 22:26nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    “Fún aláàánú ni ìwọ ó fi ara rẹ̀ hàn ni aláàánú, àti fún ẹni ìdúró ṣinṣin ní òdodo ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní ìdúró ṣinṣin ní òdodo.

  7. 2 Samuẹli 22:27nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    Fún onínú funfun ni ìwọ fi ara rẹ hàn ní funfun; àti fún ẹni wíwọ́ ni ìwọ ó fi ara rẹ hàn ní wíwọ́.

  8. 2 Samuẹli 22:28nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    Àwọn ènìyàn tí ó wà nínú ìyà ni ìwọ ó sì gbàlà; ṣùgbọ́n ojú rẹ wà lára àwọn agbéraga, láti rẹ̀ wọ́n sílẹ̀.

  9. 2 Samuẹli 22:29nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    Nítorí ìwọ ni ìmọ́lẹ̀ mi, Olúwa; Olúwa yóò sì sọ òkùnkùn mi di ìmọ́lẹ̀.

  10. 2 Samuẹli 22:30nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    Bẹ́ẹ̀ ni nítorí nípa rẹ̀ ni èmi ti la àárín ogun kọjá; nípa Ọlọ́run mi èmi ti fo odi kan.

  11. 2 Samuẹli 22:31nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    “Ọlọ́run yìí, pípé ni ọ̀nà rẹ̀; ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ti dánwò. Òun sì ni asà fún gbogbo àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé e.

  12. 2 Samuẹli 22:32nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    Nítorí ta ni Ọlọ́run, bí kò ṣe Olúwa? Ta ni àpáta, bí kò ṣe Ọlọ́run wa.

  13. 2 Samuẹli 22:33nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    Ọlọ́run alágbára ni ó fún mi ní agbára, ó sì sọ ọ̀nà mi di títọ́.

  14. 2 Samuẹli 22:34nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    Ó ṣe ẹsẹ̀ mi bí ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín; ó sì mú mi dúró ní ibi gíga mi.

  15. 2 Samuẹli 22:35nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    Ó kọ́ ọwọ́ mi ní ogun jíjà; tó bẹ́ẹ̀ tí apá mi fa ọrun idẹ.

  16. 2 Samuẹli 22:36nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    Ìwọ sì ti fún mi ní asà ìgbàlà rẹ̀; ìrẹ̀lẹ̀ rẹ̀ sì ti sọ mí di ńlá.

  17. 2 Samuẹli 22:37nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    Ìwọ sì sọ ìtẹ̀lẹ̀ di ńlá ní abẹ́ mi; tó bẹ́ẹ̀ tí ẹsẹ̀ mi kò fi yọ̀.

  18. 2 Samuẹli 22:38nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    “Èmi ti lépa àwọn ọ̀tá mi, èmi sì ti run wọ́n, èmi kò pẹ̀yìndà títí èmi fi run wọ́n.

  19. 2 Samuẹli 22:39nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    Èmi ti pa wọ́n run, èmi sì ti fọ́ wọn, wọn kò sì le dìde mọ́, wọ́n ṣubú lábẹ́ mi.

  20. 2 Samuẹli 22:40nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    Ìwọ sì ti fi agbára dì mí ní àmùrè fún ìjà; àwọn tí ó ti dìde sí mi ni ìwọ sì ti tẹ̀ lórí ba fún mi.

  21. 2 Samuẹli 22:41nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    Ìwọ sì mú àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà fún mi, èmi ó sì pa àwọn tí ó kórìíra mi run.

  22. 2 Samuẹli 22:42nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    Wọ́n wò, ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan láti gbà wọ́n; wọ́n wo Olúwa, ṣùgbọ́n kò dá àwọn lóhùn.

  23. 2 Samuẹli 22:43nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    Nígbà náà ni èmi sì gún wọn wẹ́wẹ́ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, èmi sì tẹ̀ wọ́n mọ́lẹ̀ bí ẹrẹ̀ ìta, èmi sì tẹ́ wọn gbọrọ.

  24. 2 Samuẹli 22:44nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    “Ìwọ sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìjà àwọn ènìyàn mi, ìwọ pa mi mọ́ ki èmi lè ṣe olórí àwọn àjèjì orílẹ̀-èdè. Àwọn ènìyàn tí èmi kò tí mọ̀ yóò máa sìn mí.

  25. 2 Samuẹli 22:45nǹkan bí 1018 ṣáájú Kristi

    Àwọn àjèjì wá láti tẹríba fún mi; bí wọ́n bá ti gbúròó mi, wọ́n á sì gbọ́ tèmi.