Fò sí àkóónú

Creation Era

The Great Flood

Humanity's wickedness fills the earth; God preserves Noah and his family through a catastrophic flood.

97 ẹsẹ · 1 ìwé tí a bo

Àwọn ẹsẹ láti sáà yìí

  1. Gẹnẹsisi 7:4nǹkan bí 2348 ṣáájú Kristi

    Nítorí ní ọjọ́ méje sí ìhín, èmi yóò rọ òjò sórí ilẹ̀ fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, èmi yóò sì pa gbogbo ohun alààyè tí mo ti dá run kúrò lórí ilẹ̀.”

  2. Gẹnẹsisi 7:5nǹkan bí 2348 ṣáájú Kristi

    Noa sì ṣe ohun gbogbo tí Olúwa pàṣẹ fún un.

  3. Gẹnẹsisi 7:6nǹkan bí 2348 ṣáájú Kristi

    Noa jẹ́ ọmọ ẹgbẹ̀ta (600) ọdún nígbà tí ìkún omi dé sórí ilẹ̀.

  4. Gẹnẹsisi 7:7nǹkan bí 2348 ṣáájú Kristi

    Noa àti ìyàwó rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn aya ọmọ rẹ̀ sì wọ inú ọkọ láti sá àsálà fún ìkún omi.

  5. Gẹnẹsisi 7:8nǹkan bí 2348 ṣáájú Kristi

    Méjì méjì ni àwọn ẹran tí ó mọ́ àti aláìmọ́, ti ẹyẹ àti ti gbogbo àwọn ẹ̀dá afàyàfà,

  6. Gẹnẹsisi 7:9nǹkan bí 2348 ṣáájú Kristi

    akọ àti abo ni wọ́n wọlé pẹ̀lú Noa sínú ọkọ̀ bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún Noa.

  7. Gẹnẹsisi 7:10nǹkan bí 2348 ṣáájú Kristi

    Lẹ́yìn ọjọ́ keje, ìkún omi sì dé sí ayé.

  8. Gẹnẹsisi 7:11nǹkan bí 2348 ṣáájú Kristi

    Ní ọjọ́ kẹtàdínlógún oṣù kejì, tí Noa pé ọmọ ẹgbẹ̀ta (600) ọdún, ni gbogbo ìsun ibú ya, fèrèsé ìṣàn omi ọ̀run sì ṣí sílẹ̀.

  9. Gẹnẹsisi 7:12nǹkan bí 2348 ṣáájú Kristi

    Òjò àrọ̀ìrọ̀dá sì rọ̀ fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru.

  10. Gẹnẹsisi 7:13nǹkan bí 2348 ṣáájú Kristi

    Ní ọjọ́ tí ìkún omi yóò bẹ̀rẹ̀ gan an ni Noa àti Ṣemu, Hamu àti Jafeti pẹ̀lú aya Noa àti aya àwọn ọmọ rẹ̀ wọ inú ọkọ̀.

  11. Gẹnẹsisi 7:14nǹkan bí 2348 ṣáájú Kristi

    Wọ́n mú ẹranko igbó àti ohun ọ̀sìn ní onírúurú wọn, àwọn ẹ̀dá afàyàfà àti ẹyẹ àti àwọn ohun abìyẹ́ ni onírúurú wọn.

  12. Gẹnẹsisi 7:15nǹkan bí 2348 ṣáájú Kristi

    Méjì méjì ni gbogbo ẹ̀dá tí ó ní èémí ìyè nínú wọlé pẹ̀lú Noa sínú ọkọ̀.

  13. Gẹnẹsisi 7:16nǹkan bí 2348 ṣáájú Kristi

    Gbogbo wọ́n wọlé ní takọ tabo bí Ọlọ́run ti pàṣẹ fún Noa, Olúwa sì tì wọn mọ́ inú ọkọ̀.

  14. Gẹnẹsisi 7:17nǹkan bí 2348 ṣáájú Kristi

    Òjò náà sì rọ̀ ní àrọ̀ìrọ̀dá fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru, ọkọ̀ náà sì ń léfòó lórí omi, kúrò lórí ilẹ̀ bí omi náà ti ń pọ̀ sí i.

  15. Gẹnẹsisi 7:18nǹkan bí 2348 ṣáájú Kristi

    Bí omi náà ti ń pọ̀ sí i, bẹ́ẹ̀ náà ni ọkọ̀ náà sì ń léfòó lójú omi.

  16. Gẹnẹsisi 7:19nǹkan bí 2348 ṣáájú Kristi

    Omi náà pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ó bo gbogbo àwọn òkè gíga tí ó wà lábẹ́ ọ̀run.

  17. Gẹnẹsisi 7:20nǹkan bí 2348 ṣáájú Kristi

    Omi náà kún bo àwọn òkè, bí ìwọ̀n ìgbọ̀nwọ́ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún.

  18. Gẹnẹsisi 7:21nǹkan bí 2348 ṣáájú Kristi

    Gbogbo ohun alààyè tí ó wà lórí ilẹ̀ parun: ẹyẹ, ohun ọ̀sìn, ẹranko igbó, àwọn ẹ̀dá afàyàfà àti ènìyàn.

  19. Gẹnẹsisi 7:22nǹkan bí 2348 ṣáájú Kristi

    Gbogbo ohun tí ó wà lórí ìyàngbẹ ilẹ̀ tó ní èémí ìyè ní ihò imú wọn ni ó kú.

  20. Gẹnẹsisi 7:23nǹkan bí 2348 ṣáájú Kristi

    Gbogbo ohun alààyè tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé ni a parẹ́: ènìyàn àti ẹranko, àwọn ohun tí ń rìn nílẹ̀, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run pátápátá ló ṣègbé. Noa àti àwọn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ nínú ọkọ̀ ni ó ṣẹ́kù.

  21. Gẹnẹsisi 7:24nǹkan bí 2348 ṣáájú Kristi

    Omi náà sì bo ilẹ̀ fún àádọ́jọ ọjọ́.

  22. Ọlọ́run sì rántí Noa àti ohun alààyè gbogbo tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, bí àwọn ẹranko igbó àti ohun ọ̀sìn, ó sì mú kí afẹ́fẹ́ fẹ́ sórí ilẹ̀, omi náà sì fà.

  23. Gbogbo ìsun ibú àti fèrèsé ìṣàn ọ̀run tì, òjò pẹ̀lú sì dáwọ́ rírọ̀ dúró.

  24. Omi sì bẹ̀rẹ̀ sí ní gbẹ kúrò lórí ilẹ̀, lẹ́yìn àádọ́jọ ọjọ́, ó sì ti ń fà.

  25. Ní ọjọ́ kẹtàdínlógún oṣù kejì ni ọkọ̀ náà gúnlẹ̀ sórí òkè Ararati.