circa AD 48–96
Letters to the Churches
Paul and other apostles write to strengthen, correct, and encourage the scattered churches across the Roman world.
Àwọn ẹsẹ láti sáà yìí
- Efesu 5:2nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
ẹ sì máa rìn ní ìfẹ́, gẹ́gẹ́ bí Kristi pẹ̀lú ti fẹ́ wa, tí ó sì fi ara rẹ̀ fún wa ní ọrẹ àti ẹbọ fún Ọlọ́run fún òórùn dídùn.
- Efesu 5:3nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
Ṣùgbọ́n àgbèrè àti gbogbo ìwà èérí, tàbí ojúkòkòrò, kí a má tilẹ̀ dárúkọ rẹ̀ láàrín yín mọ́, bí ó ti yẹ àwọn ènìyàn mímọ́.
- Efesu 5:4nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
Ìbá à ṣe ìwà ọ̀bùn, àti ìṣọ̀rọ̀ òmùgọ̀, tàbí ìṣẹ̀fẹ̀ àwọn ohun tí kò tọ́; ṣùgbọ́n ẹ kúkú máa dúpẹ́.
- Efesu 5:5nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
Nítorí ẹ̀yin mọ èyí dájú pé, kò sí panṣágà, tàbí aláìmọ́ ènìyàn, tàbí wọ̀bìà (tí í ṣé abọ̀rìṣà), tí yóò ni ìpín kan ni ìjọba Kristi àti Ọlọ́run.
- Efesu 5:6nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni fi ọ̀rọ̀ asán tàn yín jẹ: nítorí nípasẹ̀ nǹkan wọ̀nyí ní ìbínú Ọlọ́run fi ń bọ̀ wá sórí àwọn ọmọ aláìgbọ́ràn.
- Efesu 5:7nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
Nítorí náà ẹ má ṣe jẹ́ alájọpín pẹ̀lú wọn.
- Efesu 5:8nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
Nítorí ẹ̀yin tí jẹ́ òkùnkùn lẹ́ẹ̀kan ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ẹ̀yin dí ìmọ́lẹ̀, nípa tí Olúwa: ẹ máa rín gẹ́gẹ́ bí àwọn ọmọ ìmọ́lẹ̀
- Efesu 5:9nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
(nítorí èso Ẹ̀mí ni ìṣoore, àti òdodo àti òtítọ́).
- Efesu 5:10nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
Ẹ sì máa wádìí ohun tí í ṣe ìtẹ́wọ́gbà fún Olúwa.
- Efesu 5:11nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
Ẹ má sì ṣe bá àwọn oníṣẹ́ òkùnkùn kẹ́gbẹ́ pọ̀, ṣùgbọ́n ẹ kúkú máa bá wọn wí.
- Efesu 5:12nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
Nítorí ìtìjú tilẹ̀ ni láti máa sọ̀rọ̀ nǹkan wọ̀n-ọn-nì tí àwọn aláìgbọ́ràn ń ṣe ní ìkọ̀kọ̀.
- Efesu 5:13nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
Ṣùgbọ́n ohun gbogbo tí a tú síta ni ìmọ́lẹ̀ ń fì hàn: nítorí ohunkóhun tí ó bá fi nǹkan hàn, ìmọ́lẹ̀ ni.
- Efesu 5:14nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
Nítorí náà ni ó ṣe wí pé, “Jí, ìwọ̀ ẹni tí ó sun, sí jíǹde kúrò nínú òkú Kristi yóò sì fún ọ ní ìmọ́lẹ̀.”
- Efesu 5:15nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
Nítorí náà ẹ kíyèsi láti máa rìn ní ìwà pípé, kì í ṣé bí àwọn òmùgọ̀, ṣùgbọ́n bí àwọn ọlọ́gbọ́n;
- Efesu 5:16nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
ẹ máa ra ìgbà padà, nítorí búburú ní àwọn ọjọ́.
- Efesu 5:17nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
Nítorí náà, ẹ má ṣé jẹ aláìlóye, ṣùgbọ́n ẹ máa mòye ohun tí ìfẹ́ Olúwa jásí.
- Efesu 5:18nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
Ẹ má sí ṣe mú wáìnì ní àmupara, nínú èyí tí rúdurùdu wà; ṣùgbọ́n ẹ kún fún Ẹ̀mí Mímọ́.
- Efesu 5:19nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
Ẹ sì máa bá ara yín sọ̀rọ̀ nínú Saamu, àti orin ìyìn, àti orin Ẹ̀mí, ẹ máa kọrin, kí ẹ sì máa kọrin dídùn ní ọkàn yín sí Olúwa.
- Efesu 5:20nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
Ẹ máa dúpẹ́ nígbà gbogbo fún ohun gbogbo lọ́wọ́ Ọlọ́run, àní Baba, ní orúkọ Jesu Kristi Olúwa wá.
- Efesu 5:21nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
Ẹ máa tẹríba fún ara yín ní ìbẹ̀rù Ọlọ́run.
- Efesu 5:22nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
Ẹ̀yin aya, ẹ máa tẹríba fún àwọn ọkọ yín, gẹ́gẹ́ bí fún Olúwa.
- Efesu 5:23nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
Nítorí pé ọkọ ni ó ń ṣe orí aya, gẹ́gẹ́ bí Kristi tí i ṣe orí ìjọ, tí òun si ń ṣe ara rẹ̀, Òun sì ni Olùgbàlà rẹ̀.
- Efesu 5:24nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
Nítorí náà gẹ́gẹ́ bí ìjọ tí i tẹríba fún Kristi, bẹ́ẹ̀ sì ní kì àwọn aya máa ṣe sí ọkọ wọn ní ohun gbogbo.
- Efesu 5:25nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
Ẹ̀yin ọkọ, ẹ fẹ́ràn àwọn aya yín, gẹ́gẹ́ bí Kristi tí fẹ́ràn ìjọ, tí ó sì fi ara rẹ̀ fún un.
- Efesu 5:26nǹkan bí 64 lẹ́yìn Kristi
Kí òun lè sọ ọ́ di mímọ́ lẹ́yìn tí ó tí fi ọ̀rọ̀ wẹ̀ ẹ́ nínú agbada omí.