Fò sí àkóónú

circa 800–400 BC

The Hebrew Prophets

God speaks through Isaiah, Jeremiah, and the minor prophets—calling Israel to repentance and foretelling the coming Messiah.

3,706 ẹsẹ · 14 ìwé tí a bo

Àwọn ẹsẹ láti sáà yìí

Sẹ́ nípa ìwé
  1. Ṣùgbọ́n báwo ni yóò ṣe sinmi, nígbà tí Olúwa ti pàṣẹ fún un, nígbà tí ó ti pa á láṣẹ láti dojúkọ Aṣkeloni àti agbègbè rẹ̀.”

  2. Jeremiah 48:1nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    Nípa Moabu. Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: “Ègbé ni fún Nebo nítorí a ó parun. A dójútì Kiriataimu, a sì mú un, ojú yóò ti alágbára, a ó sì fọ́nká.

  3. Jeremiah 48:2nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    Moabu kò ní ní ìyìn mọ́, ní Heṣboni ni wọn ó pète ìparun rẹ̀, ‘Wá, kí a pa orílẹ̀-èdè náà run.’ Àti ẹ̀yin òmùgọ̀ ọkùnrin pàápàá ni a ó pa lẹ́nu mọ́, a ó fi idà lé e yín.

  4. Jeremiah 48:3nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    Gbọ́ igbe ní Horonaimu, igbe ìrora àti ìparun ńlá.

  5. Jeremiah 48:4nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    Moabu yóò di wíwó palẹ̀; àwọn ọmọdé rẹ̀ yóò kígbe síta.

  6. Jeremiah 48:5nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    Wọ́n gòkè lọ sí Luhiti, wọ́n ń sọkún kíkorò bí wọ́n ti ń lọ; ní ojú ọ̀nà sí Horonaimu igbe ìrora ìparun ni à ń gbọ́ lọ.

  7. Jeremiah 48:6nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    Sá! Àsálà fún ẹ̀mí yín; kí ẹ sì dàbí aláìní ní aginjù.

  8. Jeremiah 48:7nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    Níwọ́n ìgbà tí o gbẹ́kẹ̀lé agbára àti ọrọ̀ rẹ, a ó kó ìwọ náà ní ìgbèkùn, Kemoṣi náà yóò lọ sí ilẹ̀ ìgbèkùn pẹ̀lú àlùfáà àti àwọn aláṣẹ rẹ̀.

  9. Jeremiah 48:8nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    Gbogbo ìlú rẹ ni apanirun yóò dojúkọ, ìlú kan kò sì ní le là. Àfonífojì yóò di ahoro àti ilẹ̀ títẹ́ ni a ó run, nítorí tí Olúwa ti sọ̀rọ̀.

  10. Jeremiah 48:9nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    Fi iyọ̀ sí Moabu, nítorí yóò ṣègbé, àwọn ìlú rẹ yóò sì di ahoro láìsí ẹni tí yóò gbé inú rẹ̀.

  11. Jeremiah 48:10nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    “Ìfibú ni fún ẹni tí ó fi ìmẹ́lẹ́ ṣe iṣẹ́ Olúwa, ìfibú ni fún ẹni tí ó pa idà mọ́ fún ìtàjẹ̀ sílẹ̀.

  12. Jeremiah 48:11nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    “Moabu ti wà ní ìsinmi láti ìgbà èwe rẹ̀ wá bí i ọtí wáìnì lórí gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ rẹ̀, tí a kò dà láti ìgò kan sí èkejì kò tí ì lọ sí ilẹ̀ ìgbèkùn rí. Ó dùn lẹ́nu bí ó ti yẹ, òórùn rẹ̀ kò yí padà.

  13. Jeremiah 48:12nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    Ṣùgbọ́n ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “nígbà tí n ó rán àwọn tí ó n da ọtí láti inú àwọn ìgò tí wọ́n ó sì dà á síta; wọn ó sọ àwọn ìgò rẹ̀ di òfo, wọn ó sì fọ́ àwọn ife rẹ̀.

  14. Jeremiah 48:13nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    Nígbà náà Moabu yóò sì tú u nítorí Kemoṣi, bí ojú ti í ti ilé Israẹli nígbà tí ó gbẹ́kẹ̀lé Beteli.

  15. Jeremiah 48:14nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    “Báwo ni o ṣe lè sọ pé, ‘Ajagun ni wá, alágbára ní ogun jíjà’?

  16. Jeremiah 48:15nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    A ó pa Moabu run, a ó sì gba àwọn ìlú rẹ̀; a ó sì dúńbú àwọn arẹwà ọkùnrin rẹ̀,” ni ọba wí, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun.

  17. Jeremiah 48:16nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    “Ìṣubú Moabu súnmọ́; ìpọ́njú yóò dé kánkán.

  18. Jeremiah 48:17nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    Ẹ dárò fún, gbogbo ẹ̀yin tí ó yí i ká gbogbo ẹ̀yin tí ẹ mọ bí ó ti ní òkìkí tó. Ẹ sọ pé, ‘Báwo ni ọ̀pá agbára rẹ títóbi tí ó sì lógo ṣe fọ́!’

  19. Jeremiah 48:18nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    “Sọ̀kalẹ̀ níbi ògo rẹ, kí o sì jókòó ní ilẹ̀ gbígbẹ, ẹ̀yin olùgbé ọmọbìnrin Diboni, nítorí tí ẹni tí ó pa Moabu run yóò dojúkọ ọ́ yóò sì pa àwọn ìlú olódi rẹ run.

  20. Jeremiah 48:19nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    Dúró lẹ́bàá ọ̀nà kí o sì wòran, ìwọ tí ń gbé ní Aroeri. Bí ọkùnrin tí ó sálọ àti obìnrin tí ó ń sá àsálà ‘Kí ni ohun tí ó ṣẹlẹ̀?’

  21. Jeremiah 48:20nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    Ojú ti Moabu nítorí tí a wó o lulẹ̀. Ẹ hu, kí ẹ sì kígbe! Ẹ kéde rẹ̀ ní Arnoni pé, a pa Moabu run.

  22. Jeremiah 48:21nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    Ìdájọ́ ti dé sí àwọn òkè pẹrẹsẹ, sórí Holoni, Jahisa àti Mefaati,

  23. Jeremiah 48:22nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    sórí Diboni, Nebo àti Beti-Diblataimu,

  24. Jeremiah 48:23nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    sórí Kiriataimu, Beti-Gamu àti Beti-Meoni,

  25. Jeremiah 48:24nǹkan bí 584 ṣáájú Kristi

    sórí Kerioti àti Bosra, sórí gbogbo ìlú Moabu, nítòsí àti ní ọ̀nà jíjìn.