Fò sí àkóónú

circa 1446 BC

Sinai & The Law

God meets Israel at Mount Sinai, reveals the Ten Commandments, and establishes the Tabernacle and the priestly covenant.

1,657 ẹsẹ · 2 ìwé tí a bo

Àwọn ẹsẹ láti sáà yìí

Sẹ́ nípa ìwé
  1. Eksodu 26:13nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    Aṣọ títa àgọ́ náà yóò jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ kan gígùn ní ìhà méjèèjì, èyí tí ó kù yóò rọ̀ sórí ìhà àgọ́ náà láti fi bò ó.

  2. Eksodu 26:14nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    Ìwọ ó sì ṣe ìbòrí awọ àgbò tí a rì ní pupa fún àgọ́ náà, kí ó sì ṣe ìbòrí awọ seali sórí rẹ̀.

  3. Eksodu 26:15nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    “Ìwọ ó sì ṣe pákó igi kasia tí ó dúró òró fún àgọ́ náà.

  4. Eksodu 26:16nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    Kí pákó kọ̀ọ̀kan jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́wàá ní gígùn àti ìgbọ̀nwọ́ kan ààbọ̀ ní fífẹ̀.

  5. Eksodu 26:17nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    Pẹ̀lú ìtẹ̀bọ̀ méjì ni kí ó kọjú sí ara wọn. Ṣe gbogbo àwọn pákó àgọ́ náà bí èyí.

  6. Eksodu 26:18nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    Ìwọ ó sì ṣe ogún pákó sí ìhà gúúsù àgọ́ náà,

  7. Eksodu 26:19nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    ìwọ ó sì ṣe ogójì ìhà ìtẹ̀bọ̀ fàdákà kí ó lọ sí ìsàlẹ̀ wọn. Méjì fún pákó kọ̀ọ̀kan, ọ̀kan ní ìsàlẹ̀ ìtẹ̀bọ̀ kọ̀ọ̀kan.

  8. Eksodu 26:20nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    Àti ìhà kejì, ni ìhà àríwá àgọ́ náà, ṣe ogún pákó síbẹ̀

  9. Eksodu 26:21nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    àti ogójì ihò ìtẹ̀bọ̀ fàdákà méjì ní abẹ́ pákó kọ̀ọ̀kan.

  10. Eksodu 26:22nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    Kí ìwọ kí ó ṣe pákó mẹ́fà sì ìkangun, ní ìkangun ìhà ìwọ̀-oòrùn àgọ́ náà,

  11. Eksodu 26:23nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    kí o sì ṣe pákó méjì fún igun ní ìhà ẹ̀yìn.

  12. Eksodu 26:24nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    Ní igun méjèèjì yìí, wọ́n gbọdọ̀ jẹ́ méjì láti ìdí dé orí rẹ̀, a ó sì so wọ́n pọ̀ sí òrùka kan: méjèèjì yóò sì rí bákan náà.

  13. Eksodu 26:25nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    Wọn ó sì jẹ́ pákó mẹ́jọ, àti ihò ìtẹ̀bọ̀ fàdákà mẹ́rìnlélógún, méjì wà ní ìsàlẹ̀ ọ̀kọ̀ọ̀kan.

  14. Eksodu 26:26nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    “Ìwọ ó sì ṣe ọ̀pá ìdábùú igi kasia; márùn-ún fún pákó ìhà kan àgọ́ náà,

  15. Eksodu 26:27nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    márùn-ún fún àwọn ìhà kejì, àti márùn-ún fún pákó ni ìhà ìwọ̀-oòrùn ní ìhà ẹ̀yìn àgọ́ náà.

  16. Eksodu 26:28nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    Ọ̀pá ìdábùú àárín ni agbede-méjì gbọdọ̀ tàn láti ìkangun dé ìkangun pákó náà.

  17. Eksodu 26:29nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    Ìwọ́ ó sì bo àwọn pákó náà pẹ̀lú wúrà, kí o sì ṣe òrùka wúrà kí ó lè di ọ̀pá ìdábùú mu. Kí o sì tún bo ọ̀pá ìdábùú náà pẹ̀lú wúrà.

  18. Eksodu 26:30nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    “Gbé àgọ́ náà ró gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ tí a fihàn ọ́ lórí òkè.

  19. Eksodu 26:31nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    “Ìwọ ó sì ṣe aṣọ ìgélé aláró, àti elése àlùkò, àti òdòdó, àti ọ̀gbọ̀ olókùn wẹ́wẹ́ tí í ṣe ọlọ́nà, tí òun ti àwọn kérúbù ni kí á ṣe é.

  20. Eksodu 26:32nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    Ìwọ yóò sì fi rọ̀ sára òpó tí ó di igi kasia mẹ́rin ró tí a fi wúrà bò, tí ó dúró lórí ihò ìtẹ̀bọ̀ mẹ́rin mẹ́rin.

  21. Eksodu 26:33nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    Ṣo aṣọ títa náà sí ìsàlẹ̀ àwọn ìkọ́, kí o sì gbé àpótí ẹ̀rí sí ẹ̀gbẹ́ aṣọ títa náà. Aṣọ títa náà yóò pínyà Ibi Mímọ́ kúrò ní Ibi Mímọ́ Jùlọ.

  22. Eksodu 26:34nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    Fi ìtẹ́ àánú bo àpótí ẹ̀rí náà ni Ibi Mímọ́ Jùlọ.

  23. Eksodu 26:35nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    Gbé tábìlì náà sí ìta aṣọ títa náà sí ìhà gúúsù àgọ́ náà, kí o sì gbé ọ̀pá fìtílà sí òdìkejì rẹ̀ ní ìhà àríwá.

  24. Eksodu 26:36nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    “Fún ti ẹnu-ọ̀nà àgọ́ náà, ìwọ yóò ṣe aṣọ títa aláró, elése àlùkò, ti òdòdó àti ti ọ̀gbọ̀ olókùn wíwẹ́ tí a fi iṣẹ́ abẹ́rẹ́ ṣe.

  25. Eksodu 26:37nǹkan bí 1491 ṣáájú Kristi

    Ìwọ ó sì ṣe ìkọ́ wúrà fún aṣọ títa yìí, àti òpó igi ṣittimu márùn-ún tí a sì fi wúrà bò. Kí o sì dà ihò ìtẹ̀bọ̀ idẹ márùn-ún fún wọn.