Fò sí àkóónú

circa 1446–1406 BC

The Wilderness Years

Forty years of wandering in the desert test Israel's faith and prepare a new generation to enter the promised land.

2,247 ẹsẹ · 2 ìwé tí a bo

Àwọn ẹsẹ láti sáà yìí

Sẹ́ nípa ìwé
  1. Deuteronomi 13:8nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    má ṣe fetí sí i, má sì dá sí i, má ṣe dáàbò bò ó.

  2. Deuteronomi 13:9nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    Ṣùgbọ́n pípa ni kí o pa á. Ọwọ́ rẹ ni yóò kọ́kọ́ wà lára rẹ̀ láti pa á, lẹ́yìn náà ọwọ́ gbogbo ènìyàn.

  3. Deuteronomi 13:10nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    Sọ ọ́ ní òkúta pa nítorí pé ó gbìyànjú láti fà ọ́ kúrò lẹ́yìn Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó mú ọ jáde ti Ejibiti wá kúrò ní oko ẹrú.

  4. Deuteronomi 13:11nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    Gbogbo Israẹli yóò sì gbọ́, ẹ̀rù yóò sì bà wọ́n, kò sì sí ẹnikẹ́ni nínú yín tí yóò dán irú ibi bẹ́ẹ̀ wò mọ́.

  5. Deuteronomi 13:12nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    Bí ẹ̀yin bá gbọ́ tí a sọ nípa èyíkéyìí nínú àwọn ìlú u yín tí Olúwa Ọlọ́run yín fún un yín láti máa gbé,

  6. Deuteronomi 13:13nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    pé àwọn ènìyàn búburú, ti farahàn láàrín yín, tí ó sì ti mú kí àwọn ènìyàn ìlú wọn ṣìnà lọ, tí wọ́n wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a lọ sin ọlọ́run mìíràn.” (àwọn ọlọ́run tí ẹ kò mọ̀.)

  7. Deuteronomi 13:14nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    Kí ẹ wádìí, ẹ béèrè, kí ẹ sì tọpinpin ọ̀rọ̀ náà dájúṣáká, bí ó bá jẹ́ òtítọ́ ni, tí ó sì hàn dájú pé ìwà ìríra yìí ti ṣẹlẹ̀ láàrín yín.

  8. Deuteronomi 13:15nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    Gbogbo àwọn tí ó ń gbé ìlú náà ni kí ẹ fi idà run pátápátá. Ẹ run ún pátápátá, àti ènìyàn àti ẹran ọ̀sìn inú rẹ̀.

  9. Deuteronomi 13:16nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    Ẹ kó gbogbo ìkógun ìlú náà, sí àárín gbogbo ènìyàn, kí ẹ sun ìlú náà àti gbogbo ìkógun rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun sí Olúwa Ọlọ́run rẹ. Ó gbọdọ̀ wà ní píparun láéláé, ẹnikẹ́ni kò gbọdọ̀ tún un kọ.

  10. Deuteronomi 13:17nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    A kò gbọdọ̀ rí ọ̀kan nínú àwọn ohun ìyàsọ́tọ̀ fún ìparun wọ̀n-ọn-nì lọ́wọ́ yín, kí Olúwa ba à le yípadà kúrò nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀, yóò sì ṣàánú fún un yín, yóò sì bá a yín kẹ́dùn, yóò sì mú kí ẹ pọ̀ sí i, bí ó ti fì búra ṣèlérí fún àwọn baba ńlá yín.

  11. Deuteronomi 13:18nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    Nítorí pé ẹ̀yin gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run yín, tí ẹ̀yin sì ń pa òfin rẹ̀ mọ́, tí mo ń fún un yín lónìí yìí, tí ẹ̀yin sì ń ṣe ohun tí ó tọ́ lójú rẹ̀.

  12. Deuteronomi 14:1nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    Ọmọ Olúwa Ọlọ́run yín ni ẹ̀yin jẹ́: nítorí náà, ẹ má ṣe ya ara yín ní abẹ. Ẹ má ṣe gé irun iwájú orí yín nítorí òkú.

  13. Deuteronomi 14:2nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    Nítorí pé ènìyàn mímọ́ ní ẹ jẹ́ fún Olúwa Ọlọ́run yín, nínú gbogbo ènìyàn tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, Ọlọ́run ti yàn yín láti jẹ́ ìṣúra iyebíye rẹ̀.

  14. Deuteronomi 14:3nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    Ẹ má ṣe jẹ ohun ìríra kankan.

  15. Deuteronomi 14:4nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    Àwọn wọ̀nyí ni ẹranko tí ẹ lè máa jẹ: màlúù, àgùntàn àti ewúrẹ́,

  16. Deuteronomi 14:5nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    àgbọ̀nrín, èsúró, etu, àgóró, ẹfọ̀n, ìgalà àti àgùntàn igbó.

  17. Deuteronomi 14:6nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    Ẹ lè jẹ gbogbo ẹranko tí pátákò ẹsẹ̀ rẹ̀ kì í ṣe méjì tí ó sì tún jẹ àpọ̀jẹ.

  18. Deuteronomi 14:7nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    Síbẹ̀síbẹ̀ nínú gbogbo ẹran tí ń jẹ àpọ̀jẹ tí ó sì tún ya pátákò ẹsẹ̀ tí ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ni: ìbákasẹ, ehoro, àti ẹranko tí ó dàbí ehoro tí ń gbé inú àpáta. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n jẹ àpọ̀jẹ, ṣùgbọ́n wọn kò la pátákò ẹsẹ̀, a kà wọ́n sí àìmọ́ fún yín.

  19. Deuteronomi 14:8nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    Ẹlẹ́dẹ̀ jẹ́ àìmọ́; bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ya pátákò ẹsẹ̀, kì í jẹ àpọ̀jẹ, ẹ kò gbọdọ̀ jẹ ẹran rẹ̀, ẹ kò sì gbọdọ̀ fọwọ́ kan òkú rẹ̀.

  20. Deuteronomi 14:9nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    Nínú gbogbo ẹ̀dá alààyè tí ń gbé inú omi, ẹ lè jẹ èyíkéyìí tí ó ní lẹbẹ àti ìpẹ́.

  21. Deuteronomi 14:10nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    Ṣùgbọ́n èyíkéyìí tí kò bá ní lẹbẹ àti ìpẹ́, ẹ má ṣe jẹ ẹ́, nítorí pé àìmọ́ ni wọ́n jẹ́ fún yín.

  22. Deuteronomi 14:11nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    Ẹ lè jẹ ẹyẹ tí ó bá mọ́.

  23. Deuteronomi 14:12nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    Ṣùgbọ́n ìwọ̀nyí ní ẹ kò gbọdọ̀ jẹ: idì, igún, àkàlà,

  24. Deuteronomi 14:13nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    onírúurú àṣá àti àṣá alátagbà,

  25. Deuteronomi 14:14nǹkan bí 1451 ṣáájú Kristi

    onírúurú ẹyẹ ìwò,