Fò sí àkóónú

circa 6 BC – AD 30

The Life of Jesus

The eternal Son of God enters history: born in Bethlehem, baptized in the Jordan, crucified at Golgotha, raised on the third day.

3,779 ẹsẹ · 4 ìwé tí a bo

Àwọn ẹsẹ láti sáà yìí

Sẹ́ nípa ìwé
  1. Luku 1:52nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    Ó ti mú àwọn alágbára kúrò lórí ìtẹ́ wọn, o sì gbé àwọn onírẹ̀lẹ̀ lékè.

  2. Luku 1:53nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    Ó ti fi ohun tí ó dára kún àwọn tí ebi ń pa ó sì rán àwọn ọlọ́rọ̀ padà ní òfo.

  3. Luku 1:54nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    Ó ti ran Israẹli ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ lọ́wọ́, ní ìrántí àánú rẹ̀;

  4. Luku 1:55nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    sí Abrahamu àti àwọn ìran rẹ̀ láéláé, baba wa, àti bí ó ti sọ fún àwọn baba wa.”

  5. Luku 1:56nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    Maria sì jókòó tì Elisabeti níwọ̀n oṣù mẹ́ta, ó sì padà lọ sí ilé rẹ̀.

  6. Luku 1:57nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    Nígbà tí ọjọ́ Elisabeti pé tí yóò bí; ó sì bí ọmọkùnrin kan.

  7. Luku 1:58nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    Àwọn aládùúgbò, àti àwọn ìbátan rẹ̀ gbọ́ bí Olúwa ti fi àánú ńlá hàn fún un, wọ́n sì bá a yọ̀.

  8. Luku 1:59nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    Ó sì ṣe, ní ọjọ́ kẹjọ wọ́n wá láti kọ ọmọ náà nílà; wọ́n sì fẹ́ sọ orúkọ rẹ̀ ní Sekariah, gẹ́gẹ́ bí orúkọ baba rẹ̀.

  9. Luku 1:60nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    Ìyá rẹ̀ sì dáhùn, ó ní, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Johanu ni a ó pè é.”

  10. Luku 1:61nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    Wọ́n sì wí fún un pé, “Kò sí ọ̀kan nínú àwọn ará rẹ̀ tí à ń pè ní orúkọ yìí.”

  11. Luku 1:62nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    Wọ́n sì ṣe àpẹẹrẹ sí baba rẹ̀, bí ó ti ń fẹ́ kí a pè é.

  12. Luku 1:63nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    Ó sì béèrè fún wàláà, ó sì kọ ọ wí pé, “Johanu ni orúkọ rẹ̀.” Ẹnu sì ya gbogbo wọn.

  13. Luku 1:64nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    Ẹnu rẹ̀ sì ṣí lọ́gán, okùn ahọ́n rẹ̀ sì tú, ó sì sọ̀rọ̀, ó sì ń yin Ọlọ́run.

  14. Luku 1:65nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    Ẹ̀rù sì ba gbogbo àwọn tí ń bẹ ní agbègbè wọn, a sì ròyìn gbogbo nǹkan wọ̀nyí ká gbogbo ilẹ̀ òkè Judea.

  15. Luku 1:66nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    Ó sì jẹ́ ohun ìyanu fún gbogbo àwọn tí ó gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n sì tò ó sínú ọkàn wọn, wọ́n ń wí pé, “Irú-ọmọ kín ni èyí yóò jẹ́?” Nítorí tí ọwọ́ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀.

  16. Luku 1:67nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    Sekariah baba rẹ̀ sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, ó sì sọtẹ́lẹ̀, ó ní:

  17. Luku 1:68nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    “Olùbùkún ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli; nítorí tí ó ti bojú wò, tí ó sì ti dá àwọn ènìyàn rẹ̀ nídè,

  18. Luku 1:69nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    Ó sì ti gbé ìwo ìgbàlà sókè fún wa ní ilé Dafidi ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀;

  19. Luku 1:70nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    (bí ó ti sọtẹ́lẹ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì rẹ̀ mímọ́ tipẹ́tipẹ́),

  20. Luku 1:71nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    Pé, a ó gbà wá là lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa àti lọ́wọ́ àwọn tí ó kórìíra wá.

  21. Luku 1:72nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    Láti ṣe àánú tí ó ṣèlérí fún àwọn baba wa, àti láti rántí májẹ̀mú rẹ̀ mímọ́,

  22. Luku 1:73nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    ìbúra tí ó ti bú fún Abrahamu baba wa,

  23. Luku 1:74nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    láti gbà wá lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wa, kí àwa kí ó lè máa sìn láìfòyà,

  24. Luku 1:75nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    ni ìwà mímọ́ àti ní òdodo níwájú rẹ̀, ní ọjọ́ ayé wa gbogbo.

  25. Luku 1:76nǹkan bí 5 ṣáájú Kristi

    “Àti ìwọ, ọmọ mi, wòlíì Ọ̀gá-ògo jùlọ ni a ó máa pè ọ́: nítorí ìwọ ni yóò ṣáájú Olúwa láti tún ọ̀nà rẹ̀ ṣe;