Fò sí àkóónú

Saamu114

Ọlọ́run Ṣamọ̀nà Ísírẹ́lì Jáde Kúrò ní Íjíbítì

1
Nígbà tí Israẹli jáde ní Ejibiti, ilé Jakọbu láti inú ènìyàn àjèjì èdè
2
Juda wà ní ibi mímọ́, Israẹli wà ní ìjọba.

Ìṣẹ̀dá Fèsì Sí Wíwà Ọlọ́run

3
Òkun sì rí i, ó sì wárìrì: Jordani sì padà sẹ́yìn.
4
Àwọn òkè ńlá ń fò bí àgbò àti òkè kéékèèké bí ọ̀dọ́-àgùntàn.

Ìbéèrè Fún Ìṣẹ̀dá

5
Kí ni ó ṣe ọ́, ìwọ Òkun, tí ìwọ fi wárìrì? Ìwọ Jordani, tí ìwọ fi padà sẹ́yìn?
6
Ẹ̀yin òkè ńlá kí ló dé ti ẹ fi ń fò bí àgbò, àti ẹ̀yin òkè kéékèèké bí ọ̀dọ́-àgùntàn?

Wíwà Olúwa Ń Béèrè Ẹ̀rù

7
Wárìrì, ìwọ ilẹ̀, níwájú Olúwa; ní iwájú Ọlọ́run Jakọbu
8
tí ó sọ àpáta di adágún omi, àti òkúta-ìbọn di orísun omi.
Use arrow keys to navigate
Settings

Reading Style

Typeface

Font Size 19px

Reading Width 45 chars

Options