Skip to content
Numeri 13:1-12

Numeri 13:1-12

1
Olúwa sọ fún Mose pé,
2
“Rán ènìyàn díẹ̀ láti lọ yẹ ilẹ̀ Kenaani wò èyí tí mo ti fún àwọn ọmọ Israẹli. Rán ẹnìkọ̀ọ̀kan, tí ó jẹ́ olórí láti inú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan.”
3
Mose sì rán wọn jáde láti aginjù Parani gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa. Gbogbo wọn jẹ́ olórí àwọn ènìyàn Israẹli.
4
Orúkọ wọn nìwọ̀nyí: láti inú ẹ̀yà Reubeni, Ṣammua ọmọ Sakkuri;
5
láti inú ẹ̀yà Simeoni, Ṣafati ọmọ Hori;
6
láti inú ẹ̀yà Juda, Kalebu ọmọ Jefunne;
7
láti inú ẹ̀yà Isakari, Igali ọmọ Josẹfu;
8
láti inú ẹ̀yà Efraimu, Hosea ọmọ Nuni;
9
láti inú ẹ̀yà Benjamini, Palti ọmọ Rafu;
10
láti inú ẹ̀yà Sebuluni, Daddieli ọmọ Sodi;
11
láti inú ẹ̀yà Manase (ẹ̀yà Josẹfu), Gaddi ọmọ Susi;
12
láti inú ẹ̀yà Dani, Ammieli ọmọ Gemalli;
Settings

Reading Style

Typeface

Font Size 19px

Options