Numeri 31:9-11
9
Àwọn ọmọ Israẹli sì mú gbogbo obìnrin Midiani ní ìgbèkùn àti àwọn ọmọ kékeré wọn, wọ́n sì kó gbogbo ohun ọ̀sìn wọn àti gbogbo agbo ẹran wọn àti gbogbo ẹrù wọn.
10
Wọ́n finá jó gbogbo ìlú wọn àti ibùdó wọn.
11
Wọ́n sì kó gbogbo ìní wọn, àti ènìyàn àti ẹran.