Saamu 126:3-6
3
Olúwa ṣe ohun ńlá fún wa; nítorí náà àwa ń yọ̀.
4
Olúwa mú ìkólọ wa padà, bí ìṣàn omi ní gúúsù.
5
Àwọn tí ń fi omijé fún irúgbìn yóò fi ayọ̀ ka.
6
Ẹni tí ń fi ẹkún rìn lọ, tí ó sì gbé irúgbìn lọ́wọ́, lóòtítọ́, yóò fi ayọ̀ padà wá, yóò sì ru ìtí rẹ̀.