Saamu126
Listen to this chapter
0:00
0:00
1
Orin fún ìgòkè. Nígbà tí Olúwa mú ìkólọ Sioni padà, àwa dàbí ẹni tí ó ń lá àlá.
2
Nígbà náà ni ẹnu wa kún fún ẹ̀rín, àti ahọ́n wa kọ orin; nígbà náà ni wọ́n wí nínú àwọn kèfèrí pé, Olúwa ṣe ohun ńlá fún wọn.
3
Olúwa ṣe ohun ńlá fún wa; nítorí náà àwa ń yọ̀.
4
Olúwa mú ìkólọ wa padà, bí ìṣàn omi ní gúúsù.
5
Àwọn tí ń fi omijé fún irúgbìn yóò fi ayọ̀ ka.
6
Ẹni tí ń fi ẹkún rìn lọ, tí ó sì gbé irúgbìn lọ́wọ́, lóòtítọ́, yóò fi ayọ̀ padà wá, yóò sì ru ìtí rẹ̀.
Use ← → arrow keys to navigate
Settings
Reading Style
Typeface
Font Size px
Options
Study Note