Skip to content
Numeri 1:5-19

Numeri 1:5-19

5
“Orúkọ àwọn ọkùnrin tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ nìyí: “Láti ọ̀dọ̀ Reubeni, Elisuri ọmọ Ṣedeuri.
6
Láti ọ̀dọ̀ Simeoni, Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai.
7
Láti ọ̀dọ̀ Juda, Nahiṣoni ọmọ Amminadabu.
8
Láti ọ̀dọ̀ Isakari, Netaneli ọmọ Suari.
9
Láti ọ̀dọ̀ Sebuluni, Eliabu ọmọ Heloni.
10
Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Josẹfu: láti ọ̀dọ̀ Efraimu, Eliṣama ọmọ Ammihudu. Láti ọ̀dọ̀ Manase, Gamalieli ọmọ Pedasuri.
11
Láti ọ̀dọ̀ Benjamini, Abidani ọmọ Gideoni.
12
Láti ọ̀dọ̀ Dani, Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai.
13
Láti ọ̀dọ̀ Aṣeri, Pagieli ọmọ Okanri.
14
Láti ọ̀dọ̀ Gadi, Eliasafu ọmọ Deueli.
15
Láti ọ̀dọ̀ Naftali, Ahira ọmọ Enani.”
16
Àwọn wọ̀nyí ni wọ́n yàn nínú àwùjọ ènìyàn, olórí àwọn ẹ̀yà baba wọn. Àwọn ni olórí àwọn ẹbí Israẹli.
17
Mose àti Aaroni mú àwọn ènìyàn tí a dárúkọ wọ̀nyí
18
wọ́n sì pe gbogbo àwùjọ ènìyàn Israẹli jọ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kejì. Àwọn ènìyàn sì dárúkọ baba ńlá wọn nípa ẹbí àti ìdílé wọn. Wọ́n sì ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ àwọn ọmọkùnrin ní ọ̀kọ̀ọ̀kan láti ọmọ ogún ọdún sókè,
19
gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose. Bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe kà wọ́n nínú aginjù Sinai.
Settings

Reading Style

Typeface

Font Size 19px

Options