Saamu 29:3-9
3
Ohùn Olúwa n ré àwọn omi kọjá; Ọlọ́run ògo sán àrá, Olúwa san ara.
4
Ohùn Olúwa ní agbára; ohùn Olúwa kún fún ọláńlá.
5
Ohùn Olúwa fa igi kedari; Olúwa náà ló fọ́ igi kedari Lebanoni ya.
6
Ó mú Lebanoni fo bí i ọmọ màlúù, àti Sirioni bí ọmọ àgbáǹréré.
7
Ohùn Olúwa ń ya bí ọwọ́ iná mọ̀nà.
8
Ohùn Olúwa ń mi aginjù. Olúwa mi aginjù Kadeṣi.
9
Ohùn Olúwa ní ó lọ igi óákù, ó n mú abo àgbọ̀nrín bí, ó sì bọ́ igi igbó sí ìhòhò. Àti nínú tẹmpili rẹ̀ gbogbo ohùn wí pé, “Ògo!”
Settings