Saamu 118:22-26
22
Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, ni ó di pàtàkì igun ilé;
23
Olúwa ti ṣe èyí, ó ṣe ìyanu ní ojú wa.
24
Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá: ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú rẹ̀.
25
Olúwa, gbà wá; Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.
26
Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa. Àwa ti fi ìbùkún fún ọ láti ilé Olúwa wá.
Settings