Skip to content
Numeri 1:1-16

Numeri 1:1-16

1
Olúwa bá Mose sọ̀rọ̀ ní aginjù Sinai nínú àgọ́ àjọ ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kejì ní ọdún kejì tí àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ó wí pé,
2
“Ka gbogbo àgbájọ ènìyàn Israẹli nípa ẹbí wọn, àti nípa ìdílé baba wọn, to orúkọ wọn olúkúlùkù ọkùnrin ní ọ̀kọ̀ọ̀kan.
3
Ìwọ àti Aaroni ni kí ẹ kà gbogbo ọmọkùnrin Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn láti ọmọ ogún ọdún sókè, àwọn tí ó tó lọ sójú ogun.
4
Kí ẹ mú ọkùnrin kọ̀ọ̀kan láti inú olúkúlùkù ẹ̀yà kí ó sì wá pẹ̀lú yín, kí olúkúlùkù jẹ́ olórí ilé àwọn baba rẹ̀.
5
“Orúkọ àwọn ọkùnrin tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ nìyí: “Láti ọ̀dọ̀ Reubeni, Elisuri ọmọ Ṣedeuri.
6
Láti ọ̀dọ̀ Simeoni, Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai.
7
Láti ọ̀dọ̀ Juda, Nahiṣoni ọmọ Amminadabu.
8
Láti ọ̀dọ̀ Isakari, Netaneli ọmọ Suari.
9
Láti ọ̀dọ̀ Sebuluni, Eliabu ọmọ Heloni.
10
Láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Josẹfu: láti ọ̀dọ̀ Efraimu, Eliṣama ọmọ Ammihudu. Láti ọ̀dọ̀ Manase, Gamalieli ọmọ Pedasuri.
11
Láti ọ̀dọ̀ Benjamini, Abidani ọmọ Gideoni.
12
Láti ọ̀dọ̀ Dani, Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai.
13
Láti ọ̀dọ̀ Aṣeri, Pagieli ọmọ Okanri.
14
Láti ọ̀dọ̀ Gadi, Eliasafu ọmọ Deueli.
15
Láti ọ̀dọ̀ Naftali, Ahira ọmọ Enani.”
16
Àwọn wọ̀nyí ni wọ́n yàn nínú àwùjọ ènìyàn, olórí àwọn ẹ̀yà baba wọn. Àwọn ni olórí àwọn ẹbí Israẹli.
Settings

Reading Style

Typeface

Font Size 19px

Options