Skip to content
Numeri 3:14-20

Numeri 3:14-20

14
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose ní aginjù Sinai pé,
15
“Ka àwọn ọmọ Lefi nípa ilé baba wọn àti ìdílé wọn kí o ka gbogbo ọmọkùnrin láti ọmọ oṣù kan sókè.”
16
Mose sì kà wọ́n gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa ti pa á láṣẹ fún un.
17
Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
18
Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Gerṣoni: Libni àti Ṣimei.
19
Àwọn ìdílé Kohati ni: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli.
20
Àwọn ìdílé Merari ni: Mahili àti Muṣi. Wọ̀nyí ni ìdílé Lefi gẹ́gẹ́ bí ilé baba wọn.
Settings

Reading Style

Typeface

Font Size 19px

Options