Numeri 25:16-18
16
Olúwa sì tún sọ fún Mose pé,
17
“Ka àwọn ará Midiani sí ọ̀tá, kí o sì pa wọ́n,
18
nítorí pé wọ́n ṣe sí yín gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá nígbà tí wọ́n tàn yín nípa ìṣẹ̀lẹ̀ Peori, àti arábìnrin wọn Kosbi ọmọbìnrin ìjòyè Midiani kan, obìnrin tí a pa nígbà tí àjàkálẹ̀-ààrùn ṣẹlẹ̀ nítorí Peori.”